< Jueces 12 >

1 Entonces los efraimitas fueron convocados y cruzaron el Jordán hasta Zafón. Le dijeron a Jefté: “¿Por qué fuiste a luchar contra los amonitas sin convocarnos para que fuéramos contigo? Vamos a quemar tu casa contigo dentro”.
Àwọn ọkùnrin Efraimu pe àwọn ológun wọn jáde, wọ́n sì rékọjá sí ìhà àríwá, wọ́n sì bi Jefta pé, “Èéṣe tí o fi lọ bá àwọn ará Ammoni jagun láì ké sí wa láti bá ọ lọ? Àwa yóò sun ilé rẹ mọ́ ọ lórí.”
2 “Yo era un hombre responsable de una gran lucha”, respondió Jefté. “Yo y mi pueblo estábamos luchando contra los amonitas. Cuando te pedí ayuda, no vinieron a salvarme de ellos.
Jefta dáhùn pé, “Èmi àti àwọn ènìyàn ní ìyọnu ńlá pẹ̀lú àwọn ará Ammoni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo pè yín, ẹ̀yin kò gbà mí sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn.
3 Cuando me di cuenta de que no iban a ayudarme, me hice cargo de mi propia vida y fui a luchar contra los amonitas, y el Señor me hizo victorioso sobre ellos. Entonces, ¿por qué han venido hoy a atacarme?”.
Nígbà tí mo rí i pé ẹ̀yin kò gbà mí, mo fi ẹ̀mí mi wéwu. Mó sì gòkè lọ láti bá àwọn ará Ammoni jà, Olúwa sì fún mi ní ìṣẹ́gun lórí wọn, èéṣe báyìí tí ẹ fi dìde wá lónìí láti bá mi jà?”
4 Jefté convocó a todos los hombres de Galaad y luchó contra los efraimitas. Los hombres de Galaad los mataron porque los efraimitas se burlaban de ellos, diciendo: “Ustedes los galaaditas no son más que fugitivos que viven entre Efraín y Manasés”.
Nígbà náà ni Jefta kó gbogbo ọkùnrin Gileadi jọ, ó sì bá Efraimu jà. Àwọn ọkùnrin Gileadi sì kọlù Efraimu, nítorí wọ́n ti sọtẹ́lẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ará Gileadi jẹ́ àsáwọ̀ àwọn ará Efraimu àti ti Manase.”
5 Los galaaditas tomaron el control de los vados sobre el río Jordán que conducían al territorio de Efraín, y cuando un efraimita que escapaba de la batalla venía y pedía: “Déjenme cruzar”, los galaaditas le preguntaban: “¿Eres efraimita?”; si respondían “No”,
Àwọn ará Gileadi gba à bá wọ odò Jordani tí wọ́n máa gbà lọ sí Efraimu, nígbàkígbà tí àwọn ará Efraimu bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sálọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gileadi yóò bi í pé, “Ṣé ará Efraimu ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”
6 le decían: “Di Shibboleth”. Y los que eran de Efraín, dirían“Sibboleth” porque ellos no podían pronunciarlo bien, y así los agarrarían y los matarían allí en los vados del Jordán. Un total de 42.000 fueron asesinados en esa ocasión.
wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣibolẹti.’” Tí ó bá ní, “Sibolẹti,” torí pé kò ní mọ̀ ọ́n pé dáradára, wọ́n á mú un wọn, a sì pa á ni à bá wọ odò Jordani. Àwọn ará Efraimu tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ọkùnrin.
7 Jefté dirigió a Israel como juez durante seis años. Luego murió y fue enterrado en una de las ciudades de Galaad.
Jefta ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jefta ará Gileadi kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gileadi.
8 Después de Jefté, Ibzán de Belén dirigió a Israel como juez.
Lẹ́yìn Jefta, Ibsani ará Bẹtilẹhẹmu ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
9 Tuvo treinta hijos y treinta hijas. Casó a sus hijas con hombres de otras tribus, y trajo a treinta esposas de otras tribus para que se casaran con sus hijos. Ibzán dirigió a Israel como juez durante siete años.
Ó ní ọgbọ̀n ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ibsani ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ọdún méje.
10 Luego Ibzán murió y fue enterrado en Belén.
Lẹ́yìn náà ni Ibsani kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹtilẹhẹmu.
11 Después de él, Elón de Zabulón dirigió a Israel como juez durante diez años.
Lẹ́yìn rẹ̀, Eloni ti ẹ̀yà Sebuluni ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́wàá.
12 Luego murió y fue enterrado en Ajalón, en el territorio de Zabulón.
Eloni sì kú, wọ́n sì sin ín sí Aijaloni ní ilẹ̀ Sebuluni.
13 Después de él, Abdón, hijo de Hilel, de Piratón, dirigió a Israel como juez.
Lẹ́yìn rẹ̀ ni Abdoni ọmọ Hileli tí Piratoni n ṣe àkóso Israẹli.
14 Tuvo cuarenta hijos y treinta nietos, que montaban setenta asnos. Dirigió a Israel como juez durante ocho años.
Òun ní ogójì ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọ ọmọ àwọn tí ó ń gun àádọ́rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ó ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́jọ.
15 Luego murió y fue enterrado en Piratón, en el territorio de Efraín, en la región montañosa de los amalecitas.
Abdoni ọmọ Hileli sì kú, wọ́n sin ín sí Piratoni ní ilé Efraimu ní ìlú òkè àwọn ará Amaleki.

< Jueces 12 >