< Luka 13 >

1 Ob tistem času jih je bilo tam prisotnih nekaj, ki so mu povedali o Galilejcih, katerih kri je Pilat pomešal z njihovimi žrtvami.
Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
2 Jezus pa jim odgovori in reče: »Mislite, da so bili ti Galilejci večji grešniki kakor vsi Galilejci, ker so pretrpeli te stvari?
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
3 Povem vam: ›Ne. Toda razen če se ne pokesate, boste vsi enako pokončani.‹
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
4 Ali tistih osemnajst, na katere je padel stolp v Síloi in jih usmrtil, mislite, da so bili večji grešniki od vseh ljudi, ki prebivajo v Jeruzalemu?
Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
5 Povem vam: ›Ne. Toda razen če se ne pokesate, boste vsi enako pokončani.‹«
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
6 Povedal je tudi to prispodobo: »Neki človek je imel v svojem vinogradu posajeno figovo drevo in je prišel ter na njem iskal sadeža, pa ni našel nobenega.
Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
7 Potem je rekel obrezovalcu trte svojega vinograda: ›Glej, ta tri leta sem prihajal in iskal sadu na tem figovem drevesu, pa ga nisem našel. Posekaj ga, čemú bremeni zemljo?‹
Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
8 Ta pa odgovori in mu reče: ›Gospod, pusti jo še letos, da jo okopljem in pognojim
“Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
9 in če obrodi sad, dobro, če pa ne, jo boš torej potem posekal.‹«
Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
10 In na šabat je učil v eni izmed sinagog.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
11 In glej, tam je bila ženska, ki je osemnajst let imela duha šibkosti in je bila sključena in se nikakor ni mogla sama vzravnati.
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
12 In ko jo je Jezus zagledal, jo je poklical k sebi ter ji rekel: »Ženska, odvezana si od svoje šibkosti.«
Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
13 In nanjo je položil svoje roke in takoj je postala vzravnana ter slavila Boga.
Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
14 Predstojnik sinagoge pa je odgovoril z ogorčenjem, zato ker je Jezus zdravil na šabatni dan in rekel množici: »Šest dni je, v katerih morajo ljudje delati, v teh torej pridite in bodite zdravljeni, ne pa na šabatni dan.«
Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
15 Potem mu je Gospod odgovoril in rekel: » Ti hinavec ali ne odveže vsak izmed vas na šabat svojega vola ali svojega osla od jasli in ga vodi proč napajat?
Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
16 In ali ne bi morala biti ta ženska, ki je Abrahamova hči, ki jo je imel Satan zvezano, glejte, teh osemnajst let, odvezana te vezi na šabatni dan?«
Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
17 Ko je povedal te stvari, so bili vsi njegovi nasprotniki osramočeni in vsa množica se je veselila zaradi vseh teh veličastnih stvari, ki so bile narejene po njem.
Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
18 Tedaj je rekel: »Čému je podobno Božje kraljestvo? In s čim naj ga primerjam?
Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
19 Podobno je zrnu gorčičnega semena, ki ga je človek vzel in ga vrgel na svoj vrt, in to je zraslo ter se razvilo v veliko drevo in na njegovih mladikah je prenočevala perjad neba.«
Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
20 In ponovno je rekel: »Čému naj primerjam Božje kraljestvo?
Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
21 Podobno je kvasu, ki ga je ženska vzela in skrila v treh merah moke, dokler ni bilo vse prekvašeno.«
Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
22 On pa je šel skozi mesta in vasi ter učil in potoval proti Jeruzalemu.
Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
23 Tedaj mu je nekdo rekel: »Gospod ali je malo teh, ki bodo rešeni?« On pa jim je rekel:
Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
24 »Prizadevajte si, da vstopite pri ozkih vratih, kajti povem vam, mnogi bodo poskušali vstopiti, pa ne bodo mogli.
“Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
25 Ko enkrat hišni gospodar vstane in zapre vrata, pričnete stati zunaj ter trkati na vrata, rekoč: ›Gospod, Gospod, odpri nam, ‹ on pa vam bo odgovoril in rekel: ›Ne poznam vas, od kod ste.‹
Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
26 Tedaj boste začeli govoriti: ›V tvoji prisotnosti smo jedli in pili in na naših ulicah si učil.‹
“Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
27 Toda rekel vam bo: ›Povem vam, ne vem, od kod ste; odidite od mene, vsi vi delavci krivičnosti.‹
“Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
28 Tam bo jokanje in škripanje z zobmi, ko boste videli Abrahama, Izaka in Jakoba ter vse preroke v Božjem kraljestvu, vas same pa pahnjene ven.
“Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
29 In prišli bodo od vzhoda in od zahoda in od severa in od juga in usedli se bodo v Božjem kraljestvu.
Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
30 In glej, so zadnji, ki bodo prvi in so prvi, ki bodo zadnji.«
Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
31 Istega dne so prišli tja nekateri izmed farizejev, rekoč mu: »Pojdi ven in odidi od tod, kajti Herod te hoče ubiti.«
Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
32 On pa jim je rekel: »Pojdite in povejte temu lisjaku: ›Glej, izganjam hudiče in ozdravljam danes in jutri, tretji dan pa bom dovršen.‹
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
33 Vendar moram danes in jutri in naslednji dan hoditi, kajti ni mogoče, da prerok umre zunaj Jeruzalema.
Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
34 Oh Jeruzalem, Jeruzalem, ki ubijaš preroke in kamnaš tiste, ki so poslani k tebi; kako pogosto sem hotel zbrati tvoje otroke skupaj, kakor koklja zbira svoj zarod pod svoje peruti, pa niste hoteli!
“Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
35 Glejte, vaša hiša vam ostane zapuščena in resnično vam pravim: ›Ne boste me videli, dokler ne pride čas, ko boste rekli: ›Blagoslovljen je, kdor prihaja v Gospodovem imenu.‹«
Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”

< Luka 13 >