< Sodniki 7 >

1 Potem je Jerubáal, ki je Gideón in vse ljudstvo, ki je bilo z njim, vstalo zgodaj in se utaborilo poleg vodnjaka Haród, tako da je bila vojska Midjáncev na njihovi severni strani, v dolini pri Moréjevem hribu.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
2 Gospod je rekel Gideónu: »Ljudstva, ki je s teboj, je zame preveč, da bi Midjánce izročil v njihove roke, da se ne bi Izrael poveličeval zoper mene, rekoč: ›Moja lastna roka me je rešila.‹«
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
3 Zdaj torej pojdi, razglasi v ušesa ljudstva, rekoč: ›Kdorkoli je boječ in se boji, naj se vrne in zgodaj odide z gore Gileád.‹« In tam se jih je izmed ljudstva vrnilo dvaindvajset tisoč, ostalo pa jih je deset tisoč.
sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
4 Gospod je rekel Gideónu: »Ljudstva je še preveč. Privedi jih dol k vodi in tam ti jih bom preizkusil.« Zgodilo se bo, da o komer ti rečem: ›Ta bo šel s teboj, ‹ bo ta isti šel s teboj; in o komer ti rečem: ›Ta ne bo šel s teboj, ‹ ta isti ne bo šel.«
Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
5 Tako je ljudstvo privedel dol k vodi in Gospod je rekel Gideónu: »Kdorkoli s svojim jezikom sreba vodo, kakor sreba pes, tega boš postavil poleg sebe, podobno vsakega, ki poklekne dol na svoja kolena, da bi pil.«
Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
6 Število tistih, ki so srebali s pristavljanjem svoje roke k svojim ustom, je bilo tristo mož, toda vsi drugi izmed ljudstva so se upognili na svoja kolena, da pijejo vodo.
Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
7 Gospod je rekel Gideónu: »S tristo možmi, ki so srebali, vas bom rešil in Midjánce izročil v tvojo roko. Vse preostalo ljudstvo pa naj gre vsak mož k svojemu kraju.«
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
8 Tako je ljudstvo v svojo roko vzelo živež in svoje šofarje, ves preostanek Izraela pa je vsakega moža poslal k svojemu šotoru in obdržal tistih tristo mož. Midjánska vojska pa je bila pod njim v dolini.
Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
9 Iste noči se je pripetilo, da mu je Gospod rekel: »Vstani, spusti se k vojski, kajti izročil sem jo v tvojo roko.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
10 Toda če se bojiš iti dol, pojdi dol k vojski s svojim služabnikom Purájem.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
11 Slišal boš kaj govorijo. Potem se bodo tvoje roke okrepile, da greš dol k vojski.« Potem je s svojim služabnikom Purájem odšel dol k zunanjim izmed oboroženih mož, ki so bili v vojski.
kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
12 Midjánci in Amalečani in vsi otroci vzhoda pa so ležali povprek po dolini, zaradi množice podobni kobilicam in njihovih kamel je bilo zaradi množice brez števila, kakor peska ob morski obali.
Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
13 Ko je Gideón prišel, glej, je bil tam mož, ki je svojemu tovarišu povedal sanje ter rekel: »Glej, sanjal sem sanje in glej, kolač ječmenovega kruha se je privalil v midjánsko vojsko, prišel k šotoru in ga udaril, da je ta padel in ga prevrnil, da je ležal postrani.«
Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
14 Njegov tovariš je odgovoril in rekel: »To ni nič drugega kakor meč Gideóna, Joáševega sina, moža iz Izraela, kajti v njegovo roko je Bog izročil Midjánce in vso vojsko.«
Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
15 Bilo je tako, ko je Gideón slišal pripovedovanje sanj in njeno razlago, da je oboževal, se vrnil v Izraelovo vojsko in rekel: »Vstanite, kajti Gospod je v vašo roko izročil midjánsko vojsko.«
Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
16 Tristo mož je razdelil na tri skupine in v roko vsakega moža položil šofar s praznimi lončenimi vrči in svetilkami znotraj vrčev.
Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
17 Rekel jim je: »Glejte mene in storite podobno. In glejte, ko pridem k robu tabora, se bo zgodilo, da kakor storim jaz, boste tako storili tudi vi.
Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
18 Ko zatrobim s šofarjem, jaz in vsi tisti, ki so z menoj, potem tudi vi zatrobite s šofarji na vsaki strani tabora in recite: › Meč od Gospoda in od Gideóna.‹«
Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
19 Tako so Gideón in sto mož, ki so bili z njim, prišli k robu tabora na začetku srednje straže in imeli so ravno sveže postavljeno stražo. Zatrobili so na šofarje in razbili lončene vrče, ki so bili v njihovih rokah.
Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
20 Tri skupine so trobile na šofarje in razbile lončene vrče in držale svetilke v svojih levicah in šofarje v svojih desnicah, da z njimi trobijo in kričali: »Meč od Gospoda in od Gideóna.«
Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
21 Stali so vsak mož na svojem mestu okoli tabora in vsa vojska je stekla, kričala in pobegnila.
Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
22 Tristo [jih] je trobilo na šofarje in Gospod je torej po vsej vojski naravnal meč vsakega moža zoper svojega tovariša in vojska je pobegnila do Bet Šite v Cerédi in do meje Abél Mehóle, do Tabáta.
Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
23 Izraelovi možje so se zbrali skupaj iz Neftálija, iz Aserja, iz vsega Manáseja in zasledovali Midjánce.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
24 Gideón je poslal poslance po vsej gori Efrájim, rekoč: »Pridite dol zoper Midjánce in pred njimi zasedite vode do Bet Bare in Jordana.« Potem so se vsi Efrájimovi možje zbrali skupaj in zasedli vode do Bet Bare in Jordana.
Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
25 Zajeli so dva princa izmed Midjáncev, Oréba in Zeéba. Oréba so usmrtili na Orébovi skali, Zeéba pa so usmrtili na Zeébovi vinski stiskalnici in zasledovali Midjánce ter glavi Oréba in Zeéba prinesli Gideónu, na drugo stran Jordana.
Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.

< Sodniki 7 >