< Ezra 5 >

1 Potem sta preroka, prerok Agej in Zaharija, Idójev sin, prerokovala Judom, ki so bili v Judeji in Jeruzalemu, v imenu Izraelovega Boga, celó njim.
Nígbà náà wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, láti ìran Iddo, sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí àwọn ará Júù ní Juda àti Jerusalẹmu ní orúkọ Ọlọ́run Israẹli tí ẹ̀mí rẹ̀ ń bẹ lára wọn.
2 Potem sta vstala Šealtiélov sin Zerubabél in Jocadákov sin Ješúa in začela graditi Božjo hišo, ki je v Jeruzalemu in z njima so bili Božji preroki, ki so jima pomagali.
Nígbà náà Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua ọmọ Josadaki gbáradì fún iṣẹ́ àti tún ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu kọ́. Àwọn wòlíì Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú wọn, tí wọ́n ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
3 Ob istem času je prišel k njim Tatenáj, voditelj na tej strani reke in Šetár Boznáj in njihovi družabniki in so jim rekli tako: »Kdo vam je zapovedal, da zgradite to hišo in da postavite to obzidje?«
Ní àkókò náà Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹgbẹgbẹ́ wọn lọ sí ọ̀dọ̀ wọn. Wọ́n sì béèrè pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún tẹmpili yìí kọ́ àti láti tún odi yìí mọ?”
4 Potem smo jih vprašali na ta način: »Kako je ime možem, ki delajo to zgradbo?«
Wọ́n sì tún béèrè pé, “Kí ni orúkọ àwọn ọkùnrin tí ó ń kọ́ ilé yìí?”
5 Toda oko njihovega Boga je bilo nad Judovimi starešinami, da jim niso mogli storiti, da odnehajo, dokler zadeva ni prišla k Dareju. In potem so glede te zadeve po pismu vrnili odgovor.
Ṣùgbọ́n ojú Ọlọ́run wọn wà lára àwọn àgbàgbà Júù, wọn kò sì dá wọn dúró títí ìròyìn yóò fi dè ọ̀dọ̀ Dariusi kí wọ́n sì gba èsì tí àkọsílẹ̀ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
6 Prepis pisma, ki so ga Tatenáj, voditelj na tej strani reke in Šetár Boznáj in njegovi družabniki Afarsahejci, ki so bili na tej strani reke, poslali kralju Dareju.
Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà tí Tatenai, olórí agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn. Àwọn olóyè ti agbègbè Eufurate, fi ránṣẹ́ sí ọba Dariusi.
7 Poslali so mu pismo, v katerem je bilo napisano takole: ›Kralju Dareju, ves mir.
Ìròyìn tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i kà báyìí pé, Sí ọba Dariusi, Àlàáfíà fún un yín.
8 Bodi to znano kralju, da smo šli v judejsko provinco, k hiši vélikega Boga, ki je zgrajena z velikimi kamni in tramove polagajo v zidove in to delo hitro napreduje in uspeva v njihovih rokah.
Kí ọba kí ó mọ̀ pé a lọ sí ẹ̀kún Juda, sí tẹmpili Ọlọ́run tí ó tóbi. Àwọn ènìyàn náà ń kọ́ ọ pẹ̀lú àwọn òkúta ńlá ńlá àti pẹ̀lú fífi àwọn igi sí ara ògiri. Wọ́n ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àìsimi, ó sì ń ní ìtẹ̀síwájú kíákíá lábẹ́ ìṣàkóso wọn.
9 Potem smo vprašali te starešine in jim rekli tako: ›Kdo vam je zapovedal, da gradite to hišo in da postavite te zidove?‹
A bi àwọn àgbàgbà, a sì fi ọ̀rọ̀ wá wọn lẹ́nu wò pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún ilé Olúwa yìí kọ́ àti láti tún odi rẹ̀ mọ?”
10 Vprašali smo jih tudi za njihova imena, da ti potrdimo, da lahko napišemo imena mož, ki so bili glavni izmed njih.
A sì tún béèrè orúkọ wọn pẹ̀lú, kí a lè kọ àwọn orúkọ àwọn olórí wọn sílẹ̀ kí ẹ ba à le mọ ọ́n.
11 In tako so nam vrnili odgovor, rekoč: ›Mi smo služabniki Boga nebes in zemlje in gradimo hišo, ki je bila zgrajena teh mnogo let nazaj, ki jo je veliki Izraelov kralj zgradil in postavil.
Èyí ni ìdáhùn tí wọ́n fún wa: “Àwa ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, àwa sì ń tún tẹmpili ilé Olúwa tí a ti kọ́ ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn kọ́, èyí tí ọba olókìkí kan ní Israẹli kọ́, tí ó sì parí i rẹ̀.
12 Toda potem ko so naši očetje dražili Boga nebes do besa, jih je dal v roko babilonskega kralja Nebukadnezarja, Kaldejca, ki je uničil to hišo in ljudstvo odvedel proč v Babilon.
Ṣùgbọ́n nítorí tí àwọn baba wa mú Ọlọ́run ọ̀run bínú, ó fi wọ́n lé Nebukadnessari ti Kaldea, ọba Babeli lọ́wọ́, ẹni tí ó run tẹmpili Olúwa yìí tí ó sì kó àwọn ènìyàn náà padà sí Babeli.
13 Toda v prvem letu babilonskega kralja Kira je isti kralj Kir izdal odlok, da se gradi ta Božja hiša.
“Ṣùgbọ́n ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba Kirusi ọba Babeli, ọba Kirusi pàṣẹ pé kí a tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́.
14 Tudi posode iz zlata in srebra iz Božje hiše, ki jih je Nebukadnezar vzel iz templja, ki je bil v Jeruzalemu in jih prenesel v babilonski tempelj, te je kralj Kir vzel iz babilonskega templja in izročene so bile nekomu, katerega ime je bilo Šešbacár, ki ga je postavil za voditelja
Òun tilẹ̀ kò jáde láti inú tẹmpili ní Babeli fàdákà àti ohun èlò wúrà ilé Ọlọ́run, èyí tí Nebukadnessari kó láti inú tẹmpili ní Jerusalẹmu wá sí inú tẹmpili ní Babeli. Ọba Kirusi kó wọn fún ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Ṣeṣbassari, ẹni tí ó ti yàn gẹ́gẹ́ bí i baálẹ̀,
15 in mu rekel: ›Vzemi te posode, pojdi, odnesi jih v tempelj, ki je v Jeruzalemu in naj bo Božja hiša zgrajena na svojem mestu.‹
ó sì sọ fún un pé, ‘Kó àwọn ohun èlò yìí kí o lọ, kí o sì kó wọn sí inú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, kí ẹ sì tún ilé Ọlọ́run kọ́ sí ipò o rẹ̀.’
16 Potem je prišel isti Šešbacár in položil temelj Božji hiši, ki je v Jeruzalemu in od tega časa celo do sedaj je ta v gradnji in še ni dokončana.
“Nígbà náà ni Ṣeṣbassari náà wá, ó sí fi ìpìlẹ̀ ilé Ọlọ́run tí ó wá ní Jerusalẹmu lélẹ̀, láti ìgbà náà àní títí di ìsinsin yìí ni o ti n bẹ ní kíkọ́ ṣùgbọ́n, kò sí tí ì parí tán.”
17 Zdaj torej, če se to zdi dobro kralju, naj se preišče v kraljevi zakladni hiši, ki je tam v Babilonu, če je to tako, da je bil izdan odlok kralja Kira, da se zgradi to Božjo hišo v Jeruzalemu in naj nam kralj pošlje svojo voljo glede te zadeve.‹‹
Nísinsin yìí tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí ní ilé ìṣúra ọba ní Babeli láti rí bí ọba Kirusi fi àṣẹ lélẹ̀ lóòótọ́ láti tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́ ní Jerusalẹmu. Nígbà náà jẹ́ kí ọba kó fi ìpinnu rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí ránṣẹ́ sí wa.

< Ezra 5 >