< Вторая книга Царств 14 >

1 И разуме Иоав сын Саруин, яко сердце царево преклонися ко Авессалому.
Joabu ọmọ Seruiah sì kíyèsi i, pé ọkàn ọba sì fà sí Absalomu.
2 И посла Иоав в Фекою, и взя оттуду жену мудру и рече к ней: сетуй ныне, и облецыся в ризы сетования, и не помажися елеем, и будеши яко жена сетующая о умершем дни многи:
Joabu sì ránṣẹ́ sí Tekoa, ó sì mú ọlọ́gbọ́n obìnrin kan láti ibẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, ṣe bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀, kí o sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sára, kí o má sì ṣe fi òróró pa ara, kí o sì dàbí obìnrin ti ó ti ń ṣọ̀fọ̀ fún òkú lọ́jọ́ púpọ̀.
3 и внидеши ко царю и речеши к нему по глаголу сему. И положи Иоав словеса своя во уста ея.
Kí o sì tọ ọba wá, kí o sọ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí.” Joabu sì fi ọ̀rọ̀ sí lẹ́nu.
4 И вниде жена Фекоитяныня ко царю и паде на лицы своем на землю, и поклонися ему, и рече: спаси, царю, спаси мя.
Nígbà tí obìnrin àrá Tekoa sì ń fẹ́ sọ̀rọ̀ fún ọba, ó wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀, o sí bu ọlá fún un, o sì wí pé, “Ọba, gbà mi.”
5 И рече ей царь: что ти есть? Она же рече: издавна вдова жена аз есмь, и умре муж мой:
Ọba sì bi í léèrè pé, “Kín ni o ṣe ọ́?” Òun sì dáhùn wí pé, “Nítòótọ́ opó ni èmi ń ṣe, ọkọ mi sì kú.
6 и рабе твоей два сына, и бистася оба на селе, и не бысть кто бы их разлучил, и нападе един на брата своего, и умертви его:
Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì ti ní ọmọkùnrin méjì, àwọn méjèèjì sì jọ jà lóko, kò sì si ẹni tí yóò là wọ́n, èkínní sì lu èkejì, ó sì pa á.
7 и се, воста все отечество на рабу твою и реша: дай убившаго брата своего, и умертвим его вместо души брата, егоже уби, и погубим и наследника вашего: и угасят искру мою оставшуюся, яко не оставити мужу моему останка и имене на лицы земли.
Sì wò ó, gbogbo ìdílé dìde sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Fi ẹni tí ó pa arákùnrin rẹ fún wa, àwa ó sì pa á ní ipò ẹ̀mí arákùnrin rẹ̀ tí ó pa, àwa ó sì pa àrólé náà run pẹ̀lú.’ Wọn ó sì pa iná mi tí ó kù, wọn kì yóò sì fi orúkọ tàbí ẹni tí ó kú sílẹ̀ fún ọkọ mi ní ayé.”
8 И рече царь к жене: иди здрава в дом свой, и аз заповедаю о тебе.
Ọba sì wí fún obìnrin náà pé, “Lọ sí ilé rẹ̀, èmi ó sì kìlọ̀ nítorí rẹ.”
9 И рече жена Фекоитяныня ко царю: на мне беззаконие, господи мой царю, и на дому отца моего, царь же и престол его неповинен.
Obìnrin ará Tekoa náà sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi, ọba, jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ náà wà lórí mi, àti lórí ìdílé baba mí; kí ọba àti ìtẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ aláìlẹ́bi.”
10 И рече царь: кто глаголяй к тебе, и приведеши его ко мне, и не приложит ктому коснутися ему?
Ọba sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ sí ọ, mú ẹni náà tọ̀ mí wá, òun kì yóò sì tọ́ ọ mọ́.”
11 И рече жена: да воспомянет ныне царь Господа Бога своего, внегда умножити ужика крове, еже растлити, и не имут погубити сына моего. И рече (царь): жив Господь, аще и влас падет сыну твоему с главы на землю.
Ó sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí ọba ó rántí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má ṣe ní ipá láti ṣe ìparun, kí wọn o má bá a pa ọmọ mi!” Òun sì wí pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè ọ̀kan nínú irun orí ọmọ rẹ ki yóò bọ sílẹ̀.”
12 И рече жена: да глаголет ныне раба твоя ко господину моему царю слово. Он же рече: глаголи.
Obìnrin náà sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ sọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi ọba.” Òun si wí pé, “Máa wí.”
13 И рече жена: почто помыслил еси тако о людех Божиих? Еда от уст царевых слово сие аки преступление, еже не возвратити царю отриновеннаго своего?
Obìnrin náà sì wí pé, “Nítorí kín ni ìwọ sì ṣe ro irú nǹkan yìí sí àwọn ènìyàn Ọlọ́run? Nítorí pé ní sísọ nǹkan yìí ọba ní ẹ̀bi, nítorí pé ọba kò mú ìsáǹsá rẹ̀ bọ̀ wá ilé.
14 Яко смертию умрем, и яко вода низходящая на землю, яже не соберется, и приимет Бог душу, и помышляяй спасти от Него отриновеннаго:
Nítorí pé àwa ó sá à kú, a ó sì dàbí omi tí a tú sílẹ̀ tí a kò sì lè ṣàjọ mọ́; nítorí bí Ọlọ́run kò ti gbà ẹ̀mí rẹ̀, ó sì ti ṣe ọ̀nà kí a má bá a lé ìsáǹsá rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
15 и ныне яко приидох глаголати ко царю господину моему глагол сей, яко увидят мя людие, и речет раба твоя: да глаголет убо ко господину моему царю, негли сотворит царь слово рабы своея,
“Ǹjẹ́ nítorí náà ni èmi sì ṣe wá sọ nǹkan yìí fún olúwa mi ọba, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ti dẹ́rùbà mí; ìránṣẹ́bìnrin rẹ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ èmi ó sọ fún ọba; ó lè rí bẹ́ẹ̀ pé ọba yóò ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ fún un.
16 яко услышит царь: да измет рабу свою из рук мужей ищущих погубити мя и сына моего от участия Божия:
Nítorí pé ọba ò gbọ́, láti gbà ìránṣẹ́bìnrin rẹ sílẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin náà tí ó ń fẹ́ gé èmi àti ọmọ mi pẹ̀lú kúrò nínú ilẹ̀ ìní Ọlọ́run.’
17 и речет раба твоя: да будет ныне слово господа моего царя на жертву: якоже бо Ангел Божий, тако господь мой царь, еже слышати благое и злое: и Господь Бог твой будет с тобою.
“Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ọba olúwa mi yóò sì jásí ìtùnú; nítorí bí angẹli Ọlọ́run bẹ́ẹ̀ ni olúwa mi ọba láti mọ rere àti búburú: Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.’”
18 И отвеща царь и рече к жене: никакоже да утаиши от мене глагола, о немже аз вопрошу тя. И рече жена: да глаголет убо господь мой царь.
Ọba sì dáhùn, ó sì wí fún obìnrin náà pé, “Má ṣe fi nǹkan tí èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ pamọ́ fún mi, èmi bẹ̀ ọ́.” Obìnrin náà wí pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba máa wí?”
19 И рече царь: еда рука Иоавля о всем сем с тобою? И рече жена к царю: да живет душа твоя, господи мой царю, аще есть одесную или ошуюю от всех, яже глагола господин мой царь, яко раб твой Иоав той заповеда мне, и той вложи во уста рабе твоей вся словеса сия:
Ọba sì wí pé, “Ọwọ́ Joabu kò ha wà pẹ̀lú rẹ nínú gbogbo èyí?” Obìnrin náà sì dáhùn ó sì wí pé, “Bí ẹ̀mí rẹ ti ń bẹ láààyè, olúwa mi ọba, kò sí ìyípadà sí ọwọ́ ọ̀tún, tàbí sí ọwọ́ òsì nínú gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti wí, nítorí pé Joabu ìránṣẹ́ rẹ, òun ni ó rán mi, òun ni ó sì fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ lẹ́nu.
20 за еже приити лицу глагола сего, еже сотвори раб твой Иоав слово сие: господин же мой царь мудр, якоже мудрость Ангела Божия, еже разумети вся, яже на земли.
Láti mú irú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá ni Joabu ìránṣẹ́ rẹ ṣe ṣe nǹkan yìí: olúwa mi sì gbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n angẹli Ọlọ́run, láti mọ gbogbo nǹkan tí ń bẹ̀ ní ayé.”
21 И рече царь ко Иоаву: се, ныне сотворих ти по словеси твоему сему: иди, возврати отрока Авессалома.
Ọba sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, èmi ó ṣe nǹkan yìí, nítorí náà lọ, kí o sì mú ọmọdékùnrin náà Absalomu padà wá.”
22 И паде на лицы своем Иоав на землю, и поклонися, и благослови царя. И рече Иоав: днесь позна раб твой, яко обретох благодать пред очима твоима, господи мой царю, яко сотвори господин мой царь слово раба своего.
Joabu sì wólẹ̀ ó dojú rẹ̀ bolẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì súre fún ọba. Joabu sì wí pé, “Lónìí ni ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé, èmi rí oore-ọ̀fẹ́ gbà lójú rẹ, olúwa mi, ọba, nítorí pé ọba ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀.”
23 И воста Иоав и иде в Гедсур, и приведе Авессалома во Иерусалим.
Joabu sì dìde, ó sì lọ sí Geṣuri, ó sì mú Absalomu wá sí Jerusalẹmu.
24 И рече царь: да возвратится в дом свой, лица же моего да не видит. И возвратися Авессалом в дом свой, лица же царева не виде.
Ọba sì wí pé, “Jẹ́ kí ó yípadà lọ sí ilé rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ó rí ojú mi.” Absalomu sì yípadà sí ilé rẹ̀, kò sì rí ojú ọba.
25 И якоже Авессалом не бе муж во всем Израили хвален зело: от пяты ноги его и до верха его не бе в нем порока:
Kó sì sí arẹwà kan ní gbogbo Israẹli tí à bá yìn bí Absalomu: láti àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀ kò sí àbùkù kan lára rẹ̀.
26 и внегда стрищи ему главу свою, и бысть от начала дний до дний в няже стрижашеся, яко тяжко бяше ему от них, и стригущься весяше власы главы своея двести сиклей по сиклю царскому.
Nígbà tí ó bá sì rẹ́ irun orí rẹ̀ (nítorí pé lọ́dọọdún ni òun máa ń rẹ́ ẹ. Nígbà tí ó bá wúwo fún un, òun a sì máa rẹ́ ẹ) òun sì wọn irun orí rẹ̀, ó sì jásí igba ṣékélì nínú òsùwọ̀n ọba.
27 И родишася Авессалому три сыны и дщерь едина, и имя ей Фамарь: сия бе жена добра зело взором, и бысть жена Ровоаму сыну Соломоню, и роди ему Авию.
A sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún Absalomu àti ọmọbìnrin kan ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tamari: òun sì jẹ́ obìnrin tí ó lẹ́wà lójú.
28 И седяше Авессалом во Иерусалиме два лета дний, и лица царева не виде.
Absalomu sì gbé ni ọdún méjì ní Jerusalẹmu kò sì rí ojú ọba.
29 И посла Авессалом ко Иоаву, дабы послати его ко царю, и не восхоте приити к нему: и посла второе к нему, и не восхоте приити.
Absalomu sì ránṣẹ́ sí Joabu, láti rán an sí ọba, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì ránṣẹ́ lẹ́ẹ̀kejì òun kò sì fẹ́ wá.
30 И рече Авессалом ко отроком своим: видите, часть на селе Иоавли близ мене, его тамо ячмень, идите и запалите его огнем. И запалиша раби Авессаломли часть (Иоавлю) огнем. И приидоша раби Иоавли к нему раздравше ризы своя, и реша: пожгоша раби Авессаломли часть твою огнем.
Ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, oko Joabu gbé ti èmi, ó sì ní ọkà barle níbẹ̀; ẹ lọ kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́.” Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tiná bọ oko náà.
31 И воста Иоав и прииде ко Авессалому в дом, и рече к нему: почто сожгоша раби твои часть мою огнем?
Joabu sì dìde, ó sì tọ Absalomu wá ní ilé, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi tiná bọ oko mi?”
32 И рече Авессалом ко Иоаву: се, посылах к тебе, глаголя: иди семо, и послю тя ко царю, глаголя: почто приидох из Гедсура? Лучше ми бе быти еще тамо: и ныне се, лица царева не видех: аще же есть во мне неправда, то умертви мя.
Absalomu sì dá Joabu lóhùn pé, “Wò ó, èmi ránṣẹ́ sí ọ, wí pé, ‘Wá níhìn-ín yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sọ́dọ̀ ọba, láti béèrè pé, “Kí ni èmi ti Geṣuri wá si? Ìbá sàn fún mí bí ó ṣe pé èmi wà lọ́hùn ún síbẹ̀!”’ Ǹjẹ́ nísinsin yìí jẹ́ kí èmi lọ síwájú ọba bí ó bá sì ṣe ẹ̀bi ń bẹ nínú mi, kí ó pa mí.”
33 И вниде Иоав ко царю и возвести ему. И призва Авессалома, и прииде ко царю, и поклонися ему, и паде лицем своим на землю пред лицем царевым, и облобыза царь Авессалома.
Joabu sì tọ ọba wá, ó sì rò fún un: ó sì ránṣẹ́ pe Absalomu, òun sì wá sọ́dọ̀ ọba, ó tẹríba fún un, ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀ níwájú ọba, ọba sì fi ẹnu ko Absalomu lẹ́nu.

< Вторая книга Царств 14 >