< Књига Немијина 2 >

1 А месеца Нисана године двадесете Артаксеркса цара беше вино пред њим, и ја узевши вино дадох га цару. А пре не бејах невесео пред њим.
Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
2 И рече ми цар: Што си лица невеселог, кад ниси болестан? Није друго него туга у срцу. А ја се уплаших врло.
Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
3 И рекох цару: Да је жив цар до века! Како не бих био лица невеселог, кад је град где су гробови мојих отаца опустео и врата му огњем спаљена?
ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
4 А цар ми рече: Шта хоћеш? Тада се помолих Богу небеском,
Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
5 И рекох цару: Ако је угодно цару и ако ти је мио слуга твој, пошљи ме у Јудеју у град где су гробови отаца мојих да га саградим.
mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
6 А цар ми рече, а жена његова сеђаше до њега: Колико ти времена треба на пут, и кад ћеш се вратити? И би угодно цару, и пусти ме кад му казах време.
Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
7 Потом рекох цару: Ако је угодно цару, да ми се да књига на кнезове преко реке да ме прате докле не дођем у Јудеју,
Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
8 И књига на Асафа, чувара шуме цареве да ми да дрва за брвна на врата од двора уз дом Божји и за зид градски и за кућу у коју ћу ући. И даде ми цар, јер добра рука Бога мог беше нада мном.
Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
9 И тако дођох са кнезовима преко реке, и дадох им књиге цареве. А цар посла са мном војводе и коњике.
Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
10 А кад то чу Санавалат Ороњанин и Товија, слуга Амонац, би им врло мрско што дође човек да се постара за добро синовима Израиљевим.
Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
11 Потом дођох у Јерусалим, и бих онде три дана.
Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
12 Па устах ноћу с неколико људи, а ником не казах шта ми је Бог мој дао у срце да учиним у Јерусалиму; и не имах кљусета са собом осим оног на коме јахах.
Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
13 И изиђох ноћу на врата од долине, на извор змајевски, и на врата гнојна, и разгледах зидове јерусалимске како беху разваљени и како му врата беху огњем попаљена.
Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
14 Отуда прођох на изворска врата и на царско језеро, а онде не беше места да кљусе пода мном пређе.
Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
15 Зато јахах уз поток по ноћи и разгледах зид, па се вратих на врата од долине, и тако дођох натраг.
bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
16 Али поглавари не знаху куда сам ишао ни шта сам радио, јер дотада не бејах ништа рекао ни Јудејцима ни свештеницима ни кнезовима ни поглаварима ни другима који управљаху послом.
Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
17 Зато им рекох: Видите у каквом смо злу, Јерусалим пуст и врата му попаљена огњем; дајте да зидамо зидове јерусалимске, да више не будемо руг.
Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
18 И казах им како је добра рука Бога мог нада мном и речи цареве које ми је рекао. Тада рекоше: Устанимо и зидајмо. И укрепише им се руке на добро.
Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
19 А кад то чу Санавалат Ороњанин и Товија, слуга Амонац и Гисем Арапин, подсмеваше нам се и ругаше нам се говорећи: Шта то радите? Да се нећете одметнути цару?
Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
20 А ја им одговорих и рекох: Бог небески даће нам срећу, а ми, слуге Његове устасмо и зидамо; али ви немате дела ни права ни спомена у Јерусалиму.
Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”

< Књига Немијина 2 >