< Књига пророка Јеремије 17 >

1 Грех је Јудин записан гвозденом писаљком и врхом од дијаманта, урезан је на плочи срца њиховог и на роговима олтара ваших,
“Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
2 Да се синови њихови сећају олтара њихових и лугова њихових под зеленим дрветима, на високим хумовима.
Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
3 Горо с пољем, даћу имање твоје, све благо твоје даћу да се разграби, висине твоје, за грех по свим међама твојим.
Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
4 И ти ћеш и који су с тобом оставити наследство своје, које сам ти дао, и учинићу да служиш непријатељима својим у земљи које не познајеш; јер сте распалили огањ гнева мог, који ће горети до века.
Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
5 Овако вели Господ: Да је проклет човек који се узда у човека и који ставља тело себи за мишицу, а од Господа одступа срце његово.
Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
6 Јер ће бити као врес у пустињи, који не осећа кад дође добро, него стоји у пустињи, на сувим местима у земљи сланој и у којој се не живи.
Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
7 Благо човеку који се узда у Господа и коме је Господ узданица.
“Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
8 Јер ће бити као дрво усађено крај воде и које низ поток пушта жиле своје, које не осећа кад дође припека, него му се лист зелени, и сушне године не брине се и не престаје рађати род.
Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
9 Срце је преварно више свега и опако: ко ће га познати?
Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
10 Ја Господ испитујем срца и искушавам бубреге, да бих дао свакоме према путевима његовим и по плоду дела његових.
“Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
11 Као што јаребица лежи на јајима али не излеже, тако ко сабира богатство али с неправдом, у половини дана својих оставиће га и најпосле ће бити луд.
Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
12 Место је светиње наше престо славе, високо место од почетка.
Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
13 Надо Израиљева, Господе! Сви који Те остављају нека се посраме; који одступају од мене, нека се запишу на земљи, јер оставише извор воде живе, Господа.
Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
14 Исцели ме, Господе, и бићу исцељен; избави ме, и бићу избављен, јер си Ти хвала моја.
Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
15 Гле, они ми говоре: Где је реч Господња? Нека дође.
Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
16 А ја се не затезах ићи за Тобом као пастир, и дан жалосни не желех, Ти знаш; шта је год изашло из уста мојих, пред Тобом је.
Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
17 Не буди ми страх, Ти си уточиште моје у злу.
Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
18 Нека се посраме који ме гоне, а ја не; нека се они уплаше, а ја не; пусти на њих зли дан, и двоструким поломом поломи их.
Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
19 Овако ми рече Господ: Иди, и стани на врата синова народних, на која улазе цареви Јудини и на која излазе, и на свака врата јерусалимска.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
20 И реци им: Чујте реч Господњу, цареви Јудини и сви Јудејци и сви Јерусалимљани, који улазите на ова врата.
Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
21 Овако вели Господ: Чувајте се да не носите бреме у суботу и не уносите на врата јерусалимска.
Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
22 И не износите бремена из кућа својих у суботу, и никакав посао не радите, него светите суботу, као што сам заповедио оцима вашим.
Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
23 Али не послушаше нити пригнуше уха свог, него отврднуше вратом својим да не послушају и не приме науке.
Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
24 Ако ме послушате, говори Господ, да не носите бремена на врата овог града у суботу, него светите суботу не радећи у њу никакав посао,
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
25 Тада ће улазити на врата града овог цареви и кнезови, који седе на престолу Давидовом, на колима и на коњима, они и кнезови њихови, Јудејци и Јерусалимљани, и стајаће овај град до века.
Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
26 И долазиће из градова Јудиних и из околине јерусалимске, и из земље Венијаминове, и из равнице и из гора и с југа, и доносиће жртве паљенице и приносе с даром и кадом, и жртве захвалне доносиће у дом Господњи.
Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
27 Ако ли ме не послушате да светите суботу и не носите бремена улазећи на врата јерусалимска у суботу, онда ћу распалити огањ на вратима његовим, који ће упалити дворове јерусалимске и неће се угасити.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”

< Књига пророка Јеремије 17 >