< 2 Књига Самуилова 20 >

1 А онде се деси неваљао човек, по имену Сева, син Вихријев, од Венијамина. Он затруби у трубу и рече: Ми немамо део с Давидом, ни наследство са сином Јесејевим; свак у свој шатор, о Израиљу!
Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
2 Тако сви Израиљци одступише од Давида и отидоше за Севом сином Вихријевим; људи пак од Јуде држаше се цара свог и отпратише га од Јордана до Јерусалима.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
3 А кад цар Давид дође у кућу своју у Јерусалим, узе цар десет жена иноча, које беше оставио да му чувају кућу, и метну их у затвор, где их храњаше али не легаше с њима, него осташе затворене до смрти своје и живљаху као удовице.
Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
4 Потом рече цар Амаси: Сазови ми људе од Јуде до три дана, и нађи се и ти овде.
Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
5 И отиде Амаса да сазове народ Јудин; али се забави преко рока који му беше одређен.
Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
6 А Давид рече Ависају: Сад ће нам Сева, син Вихријев, чинити горе него Авесалом. Него узми слуге господара свог, и гони га да не нађе за се који тврд град и не умакне нам из очију.
Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
7 Тако изиђоше за њим људи Јоавови, и Херетеји и Фелетеји и сви јунаци, изиђоше из Јерусалима да гоне Севу сина Вихријевог.
Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
8 И кад беху код великог камена у Гаваону, срете их Амаса. А Јоав беше опасан преко хаљине коју имаше на себи, и озго беше припасао мач уз бедрицу у корицама. И кад пође, мач му испаде.
Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
9 Тада рече Јоав Амаси: Јеси ли здраво брате? И дохвати се Јоав десном руком својом браде Амаси да га целује.
Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
10 А Амаса не узимаше на ум мач, који беше Јоаву у руци; а он га удари њим под пето ребро, и просу му црева на земљу, те од једног ударца умре. Потом Јоав и Ависај, брат његов, отидоше у потеру за Севом сином Вихријевим.
Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
11 А један од момака Јоавових стаде код њега и рече: Ко љуби Јоава и ко је Давидов, за Јоавом!
Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
12 А Амаса се ваљаше у својој крви насред пута. И видећи онај човек где се зауставља сав народ, одвуче Амасу с пута у поље и баци хаљину на њ, кад виде где се зауставља сваки ко наиђе на њ.
Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
13 И кад би уклоњен с пута прођоше сви за Јоавом да терају Севу сина Вихријевог.
Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
14 И он прође кроз сва племена Израиљева до Авела и до Ветмахе са свим Виранима, који се окупише те иђаху за њим.
Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
15 И дошавши опколише га у Авел-Вет-Маси, и ископаше опкоп око града тако да стајаху пред зидом; и сав народ што беше с Јоавом наваљиваше да обори зид.
Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
16 Тада викну једна мудра жена из града: Чујте, чујте! Кажите Јоаву: Приступи овамо да говорим с тобом.
Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
17 А кад он приступи к њој, рече жена: Јеси ли ти Јоав? А он рече: Јесам. А она рече: Послушај речи слушкиње своје. А он рече: Да чујем.
Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
18 А она рече говорећи: Од старине се говори: Ваља питати у Авелу. И тако се извршаваше.
Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
19 Ја сам један од мирних и верних градова у Израиљу, а ти хоћеш да затреш град, и то мајку у Израиљу. Зашто хоћеш да прождреш наследство Господње?
Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
20 А Јоав одговори и рече: Сачувај Боже! Сачувај Боже! Нећу да прождрем ни да раскопам.
Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
21 Није тако; него један из горе Јефремове, по имену Сева син Вихријев, подигао је руку своју на цара Давида; дајте само њега, па ћу отићи од града. А жена рече Јоаву: Ево, глава његова бациће ти се преко зида.
Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
22 И жена отиде к свему народу с мудрошћу својом; и одсекоше главу Севи, сину Вихријевом, и бацише је Јоаву. А он затруби у трубу, те се разиђоше од града свак у свој шатор. А Јоав се врати у Јерусалим к цару.
Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
23 А беше Јоав над свом војском Израиљевом; а Венаја син Јодајев беше над Хетејима и Фелетејима;
Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
24 А Адорам беше над данцима; а Јосафат син Ахилудов беше паметар;
Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
25 Сеја писар; а Садок и Авијатар свештеници.
Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
26 И Ира Јаиранин беше кнез Давиду.
Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.

< 2 Књига Самуилова 20 >