< Isus Navin 3 >

1 I usta Isus ujutru rano, i kretoše se od Sitima i doðoše do Jordana on i svi sinovi Izrailjevi, i noæiše ondje a ne prijeðoše.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.
2 A poslije tri dana proðoše upravitelji kroz oko,
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já.
3 I zapovjediše narodu govoreæi: kad vidite kovèeg zavjeta Gospoda Boga svojega i sveštenike Levite gdje ga nose, poðite i vi s mjesta svojega i idite za njim.
Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.
4 Ali neka bude daljina izmeðu vas i njega do dvije tisuæe lakata; bliže do njega ne primièite se, da biste poznali put kojim æete iæi, jer još nikada nijeste išli tijem putem.
Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́.”
5 I Isus reèe narodu: osveštajte se, jer æe sjutra uèiniti Gospod èudesa meðu vama.
Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”
6 Potom reèe Isus sveštenicima govoreæi: uzmite kovèeg zavjetni, i idite pred narodom. I uzeše kovèeg zavjetni i poðoše pred narodom.
Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.
7 A Gospod reèe Isusu: danas te poèinjem uzvišavati pred svijem Izrailjem da poznadu da æu i s tobom biti kao što sam bio s Mojsijem.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose.
8 Zato ti zapovjedi sveštenicima koji nose kovèeg zavjetni, i reci: kad doðete na kraj vode Jordana, stanite u Jordanu.
Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà, ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’”
9 I reèe Isus sinovima Izrailjevim: pristupite ovamo, i èujte rijeèi Gospoda Boga svojega.
Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
10 Potom reèe Isus: po ovom æete poznati da je Bog živi posred vas, i da æe doista odagnati ispred vas Hananeje i Heteje i Jeveje i Ferezeje i Gergeseje i Amoreje i Jevuseje:
Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín.
11 Evo, kovèeg zavjeta Gospoda svoj zemlji poæi æe pred vama preko Jordana.
Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín.
12 Zato sada izberite dvanaest ljudi iz plemena Izrailjeva, po jednoga èovjeka iz svakoga plemena.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
13 I èim sveštenici noseæi kovèeg zavjeta Gospoda Gospoda svoj zemlji stanu nogama svojim u vodi Jordanskoj, voda æe se u Jordanu rastupiti, te æe voda koja teèe ozgo stati u gomilu.
Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”
14 I kad se podiže narod iz šatora svojih da prijeðe preko Jordana, i sveštenici ponesoše kovèeg zavjetni pred narodom,
Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.
15 I kad oni što nošahu kovèeg doðoše do Jordana, i sveštenici noseæi kovèeg okvasiše noge svoje na kraju vode jer je Jordan pun preko bregova svojih za cijelo vrijeme žetve
Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi,
16 Ustavi se voda što tecijaše ozgo, i stade u jednu gomilu vrlo nadaleko, od grada Adama, koji je kraj Zaretana; a što tecijaše dolje u more kraj polja, more slano, oteèe sasvijem; i narod prelažaše prema Jerihonu.
omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko.
17 A sveštenici koji nošahu kovèeg zavjeta Gospodnjega stajahu na suhu usred Jordana tvrdo, i sav Izrailj iðaše po suhu, dokle sav narod ne prijeðe preko Jordana.
Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.

< Isus Navin 3 >