< mathiḥ 16 >

1 tadānīṁ phirūśinaḥ sidūkinaścāgatya taṁ parīkṣituṁ nabhamīyaṁ kiñcana lakṣma darśayituṁ tasmai nivēdayāmāsuḥ|
Àwọn Farisi àti àwọn Sadusi wá láti dán Jesu wò. Wọ́n ní kí ó fi àmì ńlá kan hàn àwọn ní ojú ọ̀run.
2 tataḥ sa uktavān, sandhyāyāṁ nabhasō raktatvād yūyaṁ vadatha, śvō nirmmalaṁ dinaṁ bhaviṣyati;
Ó dá wọn lóhùn pé, “Nígbà tí ó bá di àṣálẹ́, ẹ ó sọ pé, ‘Ìbá dára kí ojú ọ̀run pọ́n.’
3 prātaḥkālē ca nabhasō raktatvāt malinatvāñca vadatha, jhañbhśadya bhaviṣyati| hē kapaṭinō yadi yūyam antarīkṣasya lakṣma bōddhuṁ śaknutha, tarhi kālasyaitasya lakṣma kathaṁ bōddhuṁ na śaknutha?
Ní òwúrọ̀, ‘Ẹ̀yin yóò wí pé ọjọ́ kì yóò dára lónìí, nítorí ti ojú ọ̀run pọ́n, ó sì ṣú dẹ̀dẹ̀,’ ẹ̀yin àgàbàgebè, ẹ̀yin le sọ àmì ojú ọ̀run, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò le mọ àmì àwọn àkókò wọ̀nyí.
4 ētatkālasya duṣṭō vyabhicārī ca vaṁśō lakṣma gavēṣayati, kintu yūnasō bhaviṣyadvādinō lakṣma vinānyat kimapi lakṣma tān na darśayiyyatē| tadānīṁ sa tān vihāya pratasthē|
Ìran búburú aláìgbàgbọ́ yìí ń béèrè àmì àjèjì mélòó kàn ni ojú sánmọ̀, ṣùgbọ́n a kí yóò fún ẹnìkankan ní àmì bí kò ṣe àmì Jona.” Nígbà náà ni Jesu fi wọ́n sílẹ̀, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
5 anantaramanyapāragamanakālē tasya śiṣyāḥ pūpamānētuṁ vismr̥tavantaḥ|
Nígbà tí wọ́n dé apá kejì adágún, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ṣàkíyèsí pé wọ́n ti gbàgbé láti mú àkàrà kankan lọ́wọ́.
6 yīśustānavādīt, yūyaṁ phirūśināṁ sidūkināñca kiṇvaṁ prati sāvadhānāḥ satarkāśca bhavata|
Jesu sì kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ kíyèsára, ẹ sì ṣọ́ra, ní ti ìwúkàrà àwọn Farisi àti àwọn Sadusi.”
7 tēna tē parasparaṁ vivicya kathayitumārēbhirē, vayaṁ pūpānānētuṁ vismr̥tavanta ētatkāraṇād iti kathayati|
Wọ́n ń sọ eléyìí ni àárín ara wọn wí pé, “Nítorí tí àwa kò mú àkàrà lọ́wọ́ ni.”
8 kintu yīśustadvijñāya tānavōcat, hē stōkaviśvāsinō yūyaṁ pūpānānayanamadhi kutaḥ parasparamētad viviṁkya?
Nígbà tí ó gbọ́ ohun ti wọ́n ń sọ, Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ẹ̀yin onígbàgbọ́ kékeré, èéṣe tí ẹ̀yin ń dààmú ara yín pé ẹ̀yin kò mú oúnjẹ lọ́wọ́?
9 yuṣmābhiḥ kimadyāpi na jñāyatē? pañcabhiḥ pūpaiḥ pañcasahasrapuruṣēṣu bhōjitēṣu bhakṣyōcchiṣṭapūrṇān kati ḍalakān samagr̥hlītaṁ;
Tàbí ọ̀rọ̀ kò yé yín di ìsinsin yìí? Ẹ̀yin kò rántí pé mo bọ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn pẹ̀lú ìṣù àkàrà márùn-ún àti iye agbọ̀n tí ẹ kójọ bí àjẹkù?
10 tathā saptabhiḥ pūpaiścatuḥsahasrapuruṣēṣu bhējitēṣu kati ḍalakān samagr̥hlīta, tat kiṁ yuṣmābhirna smaryyatē?
Ẹ kò sì tún rántí ìṣù méje tí mo fi bọ́ ẹgbàajì ènìyàn àti iye agbọ̀n tí ẹ̀yín kójọ?
11 tasmāt phirūśināṁ sidūkināñca kiṇvaṁ prati sāvadhānāstiṣṭhata, kathāmimām ahaṁ pūpānadhi nākathayaṁ, ētad yūyaṁ kutō na budhyadhvē?
Èéha ṣe tí kò fi yé yín pé èmi kò sọ̀rọ̀ nípa ti àkàrà? Lẹ́ẹ̀kan sí i, mo wí fún yín, ẹ ṣọ́ra fún ìwúkàrà àwọn Farisi àti ti Sadusi.”
12 tadānīṁ pūpakiṇvaṁ prati sāvadhānāstiṣṭhatēti nōktvā phirūśināṁ sidūkināñca upadēśaṁ prati sāvadhānāstiṣṭhatēti kathitavān, iti tairabōdhi|
Nígbà náà ni ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wáyé wọn pé, kì í ṣe nípa ti ìwúkàrà ní ó sọ wí pé kí wọ́n kíyèsára, bí kò ṣe tí ẹ̀kọ́ àwọn Farisi àti Sadusi.
13 aparañca yīśuḥ kaisariyā-philipipradēśamāgatya śiṣyān apr̥cchat, yō'haṁ manujasutaḥ sō'haṁ kaḥ? lōkairahaṁ kimucyē?
Nígbà tí Jesu sì dé Kesarea-Filipi, ó bi àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi Ọmọ Ènìyàn pè?”
14 tadānīṁ tē kathitavantaḥ, kēcid vadanti tvaṁ majjayitā yōhan, kēcidvadanti, tvam ēliyaḥ, kēcicca vadanti, tvaṁ yirimiyō vā kaścid bhaviṣyadvādīti|
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwọn kan ni Johanu onítẹ̀bọmi ni, àwọn mìíràn wí pé, Elijah ni, àwọn mìíràn wí pé, Jeremiah ni, tàbí ọ̀kan nínú àwọn wòlíì.”
15 paścāt sa tān papraccha, yūyaṁ māṁ kaṁ vadatha? tataḥ śimōn pitara uvāca,
“Ṣùgbọ́n ẹyin ń kọ?” Ó bi í léèrè pé, “Ta ni ẹ̀yin ń fi mi pè?”
16 tvamamarēśvarasyābhiṣiktaputraḥ|
Simoni Peteru dáhùn pé, “Ìwọ ni Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run alààyè.”
17 tatō yīśuḥ kathitavān, hē yūnasaḥ putra śimōn tvaṁ dhanyaḥ; yataḥ kōpi anujastvayyētajjñānaṁ nōdapādayat, kintu mama svargasyaḥ pitōdapādayat|
Jesu sì wí fún un pé, “Alábùkún fún ni ìwọ Simoni ọmọ Jona, nítorí ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ kọ́ ló fi èyí hàn bí kò ṣe Baba mi tí ó ń bẹ ní ọ̀run.
18 atō'haṁ tvāṁ vadāmi, tvaṁ pitaraḥ (prastaraḥ) ahañca tasya prastarasyōpari svamaṇḍalīṁ nirmmāsyāmi, tēna nirayō balāt tāṁ parājētuṁ na śakṣyati| (Hadēs g86)
Èmi wí fún ọ, ìwọ ni Peteru àti pé orí àpáta yìí ni èmi yóò kọ́ ìjọ mi lé, àti ẹnu-ọ̀nà ipò òkú kì yóò lè borí rẹ̀. (Hadēs g86)
19 ahaṁ tubhyaṁ svargīyarājyasya kuñjikāṁ dāsyāmi, tēna yat kiñcana tvaṁ pr̥thivyāṁ bhaṁtsyasi tatsvargē bhaṁtsyatē, yacca kiñcana mahyāṁ mōkṣyasi tat svargē mōkṣyatē|
Èmi yóò fún ní àwọn kọ́kọ́rọ́ ìjọba Ọ̀run; ohun tí ìwọ bá dè ní ayé, òun ni a ó dè ní ọ̀run. Ohunkóhun tí ìwọ bá sì tú ní ayé yìí, a ó sì tú ní ọ̀run.”
20 paścāt sa śiṣyānādiśat, ahamabhiṣiktō yīśuriti kathāṁ kasmaicidapi yūyaṁ mā kathayata|
Nígbà náà ó kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ sọ fún ẹnikẹ́ni pé Òun ni Kristi náà.
21 anyañca yirūśālamnagaraṁ gatvā prācīnalōkēbhyaḥ pradhānayājakēbhya upādhyāyēbhyaśca bahuduḥkhabhōgastai rhatatvaṁ tr̥tīyadinē punarutthānañca mamāvaśyakam ētāḥ kathā yīśustatkālamārabhya śiṣyān jñāpayitum ārabdhavān|
Láti ìgbà yìí lọ, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí ṣàlàyé fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kedere nípa lílọ sí Jerusalẹmu láti jẹ ọ̀pọ̀ ìyà lọ́wọ́ àwọn àgbàgbà, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé, kí a sì pa òun, àti ní ọjọ́ kẹta, kí ó sì jíǹde.
22 tadānīṁ pitarastasya karaṁ ghr̥tvā tarjayitvā kathayitumārabdhavān, hē prabhō, tat tvattō dūraṁ yātu, tvāṁ prati kadāpi na ghaṭiṣyatē|
Peteru mú Jesu sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó bẹ̀rẹ̀ sí í bá a wí pé, “Kí a má rí i Olúwa! Èyí kì yóò ṣẹlẹ̀ sí Ọ!”
23 kintu sa vadanaṁ parāvartya pitaraṁ jagāda, hē vighnakārin, matsammukhād dūrībhava, tvaṁ māṁ bādhasē, īśvarīyakāryyāt mānuṣīyakāryyaṁ tubhyaṁ rōcatē|
Jesu pa ojú dà, ó sì wí fún Peteru pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani! Ohun ìkọ̀sẹ̀ ni ìwọ jẹ́ fún mi; ìwọ kò ro ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, bí kò ṣe èyí ti ṣe ti ènìyàn.”
24 anantaraṁ yīśuḥ svīyaśiṣyān uktavān yaḥ kaścit mama paścādgāmī bhavitum icchati, sa svaṁ dāmyatu, tathā svakruśaṁ gr̥hlan matpaścādāyātu|
Nígbà náà ni Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó sì gbé àgbélébùú rẹ̀, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
25 yatō yaḥ prāṇān rakṣitumicchati, sa tān hārayiṣyati, kintu yō madarthaṁ nijaprāṇān hārayati, sa tān prāpsyati|
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ gba ẹ̀mí rẹ̀ là, yóò sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù nítorí mi, yóò rí i.
26 mānuṣō yadi sarvvaṁ jagat labhatē nijapraṇān hārayati, tarhi tasya kō lābhaḥ? manujō nijaprāṇānāṁ vinimayēna vā kiṁ dātuṁ śaknōti?
Èrè kí ni ó jẹ́ fún ènìyàn bí ó bá jèrè gbogbo ayé yìí, tí ó sì sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù? Tàbí kí ni ènìyàn yóò fi dípò ẹ̀mí rẹ̀?
27 manujasutaḥ svadūtaiḥ sākaṁ pituḥ prabhāvēṇāgamiṣyati; tadā pratimanujaṁ svasvakarmmānusārāt phalaṁ dāsyati|
Nítorí Ọmọ Ènìyàn yóò wá nínú ògo baba rẹ pẹ̀lú àwọn angẹli rẹ̀, nígbà náà ni yóò sì san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
28 ahaṁ yuṣmān tathyaṁ vacmi, sarājyaṁ manujasutam āgataṁ na paśyantō mr̥tyuṁ na svādiṣyanti, ētādr̥śāḥ katipayajanā atrāpi daṇḍāyamānāḥ santi|
“Lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹlòmíràn wà nínú àwọn tí ó wà níhìn-ín yìí, tí kì yóò ri ikú títí wọn ó fi rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ ní ìjọba rẹ̀.”

< mathiḥ 16 >