< lūkaḥ 19 >

1 yadā yīśu ryirīhōpuraṁ praviśya tanmadhyēna gacchaṁstadā
Jesu sì wọ Jeriko lọ, ó sì ń kọjá láàrín rẹ̀.
2 sakkēyanāmā karasañcāyināṁ pradhānō dhanavānēkō
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà tí a ń pè ní Sakeu, ó sì jẹ́ olórí agbowó òde kan, ó sì jẹ́ ọlọ́rọ̀.
3 yīśuḥ kīdr̥giti draṣṭuṁ cēṣṭitavān kintu kharvvatvāllōkasaṁghamadhyē taddarśanamaprāpya
Ó sì ń fẹ́ láti rí ẹni tí Jesu jẹ́: kò sì lè rí i, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti nítorí tí òun jẹ́ ènìyàn kúkúrú.
4 yēna pathā sa yāsyati tatpathē'grē dhāvitvā taṁ draṣṭum uḍumbaratarumārurōha|
Ó sì súré síwájú, ó gun orí igi sikamore kan, kí ó bà lè rí i: nítorí tí yóò kọjá lọ níhà ibẹ̀.
5 paścād yīśustatsthānam itvā ūrddhvaṁ vilōkya taṁ dr̥ṣṭvāvādīt, hē sakkēya tvaṁ śīghramavarōha mayādya tvadgēhē vastavyaṁ|
Nígbà tí Jesu sì dé ibẹ̀, ó gbé ojú sókè, ó sì rí i, ó sì wí fún un pé, “Sakeu! Yára, kí o sì sọ̀kalẹ̀; nítorí pé èmi yóò wọ ilé rẹ lónìí.”
6 tataḥ sa śīghramavaruhya sāhlādaṁ taṁ jagrāha|
Ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbà á.
7 tad dr̥ṣṭvā sarvvē vivadamānā vaktumārēbhirē, sōtithitvēna duṣṭalōkagr̥haṁ gacchati|
Nígbà tí wọ́n sì rí i, gbogbo wọn ń kùn, wí pé, “Ó lọ bá ọkùnrin ẹlẹ́ṣẹ̀ náà ní àlejò.”
8 kintu sakkēyō daṇḍāyamānō vaktumārēbhē, hē prabhō paśya mama yā sampattirasti tadarddhaṁ daridrēbhyō dadē, aparam anyāyaṁ kr̥tvā kasmādapi yadi kadāpi kiñcit mayā gr̥hītaṁ tarhi taccaturguṇaṁ dadāmi|
Sakeu sì dìde, ó sì wí fún Olúwa pé, “Wò ó, Olúwa, ààbọ̀ ohun ìní mi ni mo fi fún tálákà; bí mo bá sì fi èké gba ohun kan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, èmi san án padà ní ìlọ́po mẹ́rin!”
9 tadā yīśustamuktavān ayamapi ibrāhīmaḥ santānō'taḥ kāraṇād adyāsya gr̥hē trāṇamupasthitaṁ|
Jesu sì wí fún un pé, “Lónìí ni ìgbàlà wọ ilé yìí, níwọ̀n bí òun pẹ̀lú ti jẹ́ ọmọ Abrahamu.
10 yad hāritaṁ tat mr̥gayituṁ rakṣituñca manuṣyaputra āgatavān|
Nítorí Ọmọ Ènìyàn dé láti wá àwọn tí ó nù kiri, àti láti gbà wọ́n là.”
11 atha sa yirūśālamaḥ samīpa upātiṣṭhad īśvararājatvasyānuṣṭhānaṁ tadaiva bhaviṣyatīti lōkairanvabhūyata, tasmāt sa śrōtr̥bhyaḥ punardr̥ṣṭāntakathām utthāpya kathayāmāsa|
Nígbà tí wọ́n sì ń gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó sì tẹ̀síwájú láti pa òwe kan, nítorí tí ó súnmọ́ Jerusalẹmu, àti nítorí tí wọn ń rò pé, ìjọba Ọlọ́run yóò farahàn nísinsin yìí.
12 kōpi mahāllōkō nijārthaṁ rājatvapadaṁ gr̥hītvā punarāgantuṁ dūradēśaṁ jagāma|
Ó sì wí pé, “Ọkùnrin ọlọ́lá kan lọ sí ìlú òkèrè láti gba ìjọba kí ó sì padà.
13 yātrākālē nijān daśadāsān āhūya daśasvarṇamudrā dattvā mamāgamanaparyyantaṁ vāṇijyaṁ kurutētyādidēśa|
Ó sì pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ mẹ́wàá, ó fi owó mina mẹ́wàá fún wọn, ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ máa ṣòwò títí èmi ó fi dé!’
14 kintu tasya prajāstamavajñāya manuṣyamēnam asmākamupari rājatvaṁ na kārayivyāma imāṁ vārttāṁ tannikaṭē prērayāmāsuḥ|
“Ṣùgbọ́n àwọn ará ìlù rẹ̀ kórìíra rẹ̀, wọ́n sì rán ikọ̀ tẹ̀lé e, wí pé, ‘Àwa kò fẹ́ kí ọkùnrin yìí jẹ ọba lórí wa.’
15 atha sa rājatvapadaṁ prāpyāgatavān ēkaikō janō bāṇijyēna kiṁ labdhavān iti jñātuṁ yēṣu dāsēṣu mudrā arpayat tān āhūyānētum ādidēśa|
“Nígbà tí ó gba ìjọba tan, tí ó padà dé, ó pàṣẹ pé, kí a pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọ̀nyí tí òun ti fi owó fún wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí kí ó le mọ iye èrè tí olúkúlùkù ti jẹ nínú iṣẹ́ òwò wọn.
16 tadā prathama āgatya kathitavān, hē prabhō tava tayaikayā mudrayā daśamudrā labdhāḥ|
“Èyí èkínní sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina mẹ́wàá sí i.’
17 tataḥ sa uvāca tvamuttamō dāsaḥ svalpēna viśvāsyō jāta itaḥ kāraṇāt tvaṁ daśanagarāṇām adhipō bhava|
“Olúwa rẹ̀ sì wí fún un pé, ‘O ṣeun, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere! Nítorí tí ìwọ ṣe olóòtítọ́ ní ohun kínkínní, gba àṣẹ lórí ìlú mẹ́wàá.’
18 dvitīya āgatya kathitavān, hē prabhō tavaikayā mudrayā pañcamudrā labdhāḥ|
“Èyí èkejì sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina márùn.’
19 tataḥ sa uvāca, tvaṁ pañcānāṁ nagarāṇāmadhipati rbhava|
“Olúwa rẹ sì wí fún un pẹ̀lú pé, ‘Ìwọ pẹ̀lú joyè ìlú márùn-ún!’
20 tatōnya āgatya kathayāmāsa, hē prabhō paśya tava yā mudrā ahaṁ vastrē baddhvāsthāpayaṁ sēyaṁ|
“Òmíràn sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, wò ó owó mina rẹ tí ń bẹ lọ́wọ́ mi ni mo dì sínú aṣọ pélébé kan;
21 tvaṁ kr̥paṇō yannāsthāpayastadapi gr̥hlāsi, yannāvapastadēva ca chinatsi tatōhaṁ tvattō bhītaḥ|
nítorí mo bẹ̀rù rẹ, àti nítorí tí ìwọ ṣe òǹrorò ènìyàn, ìwọ a máa mú èyí tí ìwọ kò fi lélẹ̀, ìwọ a sì máa ká èyí tí ìwọ kò gbìn!’
22 tadā sa jagāda, rē duṣṭadāsa tava vākyēna tvāṁ dōṣiṇaṁ kariṣyāmi, yadahaṁ nāsthāpayaṁ tadēva gr̥hlāmi, yadahaṁ nāvapañca tadēva chinadmi, ētādr̥śaḥ kr̥paṇōhamiti yadi tvaṁ jānāsi,
“Olúwa rẹ sì wí fún un pé, ‘Ní ẹnu ara rẹ náà ni èmi ó ṣe ìdájọ́ rẹ, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, ìwọ mọ̀ pé òǹrorò ènìyàn ni mí, pé, èmi a máa mú èyí tí èmi kò fi lélẹ̀ èmi a sì máa ká èyí tí èmi kò gbìn.
23 tarhi mama mudrā baṇijāṁ nikaṭē kutō nāsthāpayaḥ? tayā kr̥tē'ham āgatya kusīdēna sārddhaṁ nijamudrā aprāpsyam|
Èéha sì ti ṣe tí ìwọ kò fi owó mi pamọ́ sí ilé ìfowópamọ́, pé nígbà tí mo bá dé, èmi ìbá ti béèrè rẹ̀ pẹ̀lú èlé?’
24 paścāt sa samīpasthān janān ājñāpayat asmāt mudrā ānīya yasya daśamudrāḥ santi tasmai datta|
“Ó sì wí fún àwọn tí ó dúró létí ibẹ̀ pé, ‘Ẹ gba owó mina náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí ẹ sì fi í fún ẹni tí ó ní owó mina mẹ́wàá.’
25 tē prōcuḥ prabhō'sya daśamudrāḥ santi|
“Wọ́n sì wí fún un pé, ‘Olúwa, ó ní owó mina mẹ́wàá.’
26 yuṣmānahaṁ vadāmi yasyāśrayē vaddhatē 'dhikaṁ tasmai dāyiṣyatē, kintu yasyāśrayē na varddhatē tasya yadyadasti tadapi tasmān nāyiṣyatē|
“Mo wí fún yín pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní, ni a ó fi fún, àti lọ́dọ̀ ẹni tí kò ní èyí tí ó ní pàápàá a ó gbà á lọ́wọ́ rẹ̀.
27 kintu mamādhipatitvasya vaśatvē sthātum asammanyamānā yē mama ripavastānānīya mama samakṣaṁ saṁharata|
Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá mi wọ̀nyí, tí kò fẹ́ kí èmi jẹ ọba lórí wọn ẹ mú wọn wá ìhín yìí, kí ẹ sì pa wọ́n níwájú mi!’”
28 ityupadēśakathāṁ kathayitvā sōgragaḥ san yirūśālamapuraṁ yayau|
Nígbà tí ó sì ti wí nǹkan wọ̀nyí tan, ó lọ síwájú, ó ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
29 tatō baitphagībaithanīyāgrāmayōḥ samīpē jaitunādrērantikam itvā śiṣyadvayam ityuktvā prēṣayāmāsa,
Ó sì ṣe, nígbà tí ó súnmọ́ Betfage àti Betani ní òkè tí a ń pè ní òkè olifi, ó rán àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
30 yuvāmamuṁ sammukhasthagrāmaṁ praviśyaiva yaṁ kōpi mānuṣaḥ kadāpi nārōhat taṁ garddabhaśāvakaṁ baddhaṁ drakṣyathastaṁ mōcayitvānayataṁ|
Wí pé, “Ẹ lọ sí ìletò tí ó kọjú sí yín; nígbà tí ẹ̀yin bá wọ̀ ọ́ lọ, ẹ̀yin ó rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan tí a so, tí ẹnikẹ́ni kò gùn rí, ẹ tú u, kí ẹ sì fà á wá.
31 tatra kutō mōcayathaḥ? iti cēt kōpi vakṣyati tarhi vakṣyathaḥ prabhēratra prayōjanam āstē|
Bí ẹnikẹ́ni bá sì bi yín pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tú u?’ Kí ẹ̀yin wí báyìí pé, ‘Olúwa ń fẹ́ lò ó.’”
32 tadā tau praritau gatvā tatkathānusārēṇa sarvvaṁ prāptau|
Àwọn tí a rán sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó ti wí fún wọn.
33 gardabhaśāvakamōcanakālē tatvāmina ūcuḥ, gardabhaśāvakaṁ kutō mōcayathaḥ?
Bí wọ́n sì ti ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn Olúwa rẹ̀ bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà?”
34 tāvūcatuḥ prabhōratra prayōjanam āstē|
Wọ́n sì wí pé, “Olúwa fẹ́ lò ó.”
35 paścāt tau taṁ gardabhaśāvakaṁ yīśōrantikamānīya tatpr̥ṣṭhē nijavasanāni pātayitvā tadupari yīśumārōhayāmāsatuḥ|
Wọ́n sì fà á tọ Jesu wá, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sí ẹ̀yìn ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, wọ́n sì gbé Jesu kà á.
36 atha yātrākālē lōkāḥ pathi svavastrāṇi pātayitum ārēbhirē|
Bí ó sì ti ń lọ wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà.
37 aparaṁ jaitunādrērupatyakām itvā śiṣyasaṁghaḥ pūrvvadr̥ṣṭāni mahākarmmāṇi smr̥tvā,
Bí ó sì ti súnmọ́ etí ibẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè olifi, gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í yọ̀, wọ́n sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run, nítorí iṣẹ́ ńlá gbogbo tí wọ́n ti rí,
38 yō rājā prabhō rnāmnāyāti sa dhanyaḥ svargē kuśalaṁ sarvvōccē jayadhvani rbhavatu, kathāmētāṁ kathayitvā sānandam ucairīśvaraṁ dhanyaṁ vaktumārēbhē|
wí pé, “Olùbùkún ni ọba tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Àlàáfíà ní ọ̀run, àti ògo ni òkè ọ̀run!”
39 tadā lōkāraṇyamadhyasthāḥ kiyantaḥ phirūśinastat śrutvā yīśuṁ prōcuḥ, hē upadēśaka svaśiṣyān tarjaya|
Àwọn kan nínú àwọn Farisi nínú àwùjọ náà sì wí fún un pé, “Olùkọ́ bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ wí.”
40 sa uvāca, yuṣmānahaṁ vadāmi yadyamī nīravāstiṣṭhanti tarhi pāṣāṇā ucaiḥ kathāḥ kathayiṣyanti|
Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí fún wọn pé, “Mo wí fún yín, bí àwọn wọ̀nyí bá pa ẹnu wọn mọ́, àwọn òkúta yóò kígbe sókè.”
41 paścāt tatpurāntikamētya tadavalōkya sāśrupātaṁ jagāda,
Nígbà tí ó sì súnmọ́ etílé, ó síjú wo ìlú náà, ó sọkún sí i lórí,
42 hā hā cēt tvamagrē'jñāsyathāḥ, tavāsminnēva dinē vā yadi svamaṅgalam upālapsyathāḥ, tarhyuttamam abhaviṣyat, kintu kṣaṇēsmin tattava dr̥ṣṭēragōcaram bhavati|
Ó ń wí pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ̀, lónìí yìí, àní ìwọ, ohun tí í ṣe tí àlàáfíà rẹ! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n pamọ́ kúrò lójú rẹ.
43 tvaṁ svatrāṇakālē na manō nyadhatthā iti hētō ryatkālē tava ripavastvāṁ caturdikṣu prācīrēṇa vēṣṭayitvā rōtsyanti
Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ fún ọ, tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò mọ odi bèbè yí ọ ká, àní tí wọn yóò sì yí ọ ká, wọn ó sì ká ọ mọ́ níhà gbogbo.
44 bālakaiḥ sārddhaṁ bhūmisāt kariṣyanti ca tvanmadhyē pāṣāṇaikōpi pāṣāṇōpari na sthāsyati ca, kāla īdr̥śa upasthāsyati|
Wọn ó sì wó ọ palẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ; wọn kì yóò sì fi òkúta kan sílẹ̀ lórí ara wọn; nítorí ìwọ kò mọ ọjọ́ ìbẹ̀wò rẹ.”
45 atha madhyēmandiraṁ praviśya tatratyān krayivikrayiṇō bahiṣkurvvan
Ó sì wọ inú tẹmpili lọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lé àwọn tí ń tà nínú rẹ̀ sóde;
46 avadat madgr̥haṁ prārthanāgr̥hamiti lipirāstē kintu yūyaṁ tadēva cairāṇāṁ gahvaraṁ kurutha|
Ó sì wí fún wọn pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ilé mi yóò jẹ́ ilé àdúrà?’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ihò àwọn ọlọ́ṣà.”
47 paścāt sa pratyahaṁ madhyēmandiram upadidēśa; tataḥ pradhānayājakā adhyāpakāḥ prācīnāśca taṁ nāśayituṁ cicēṣṭirē;
Ó sì ń kọ́ni lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, àti àwọn olórí àwọn ènìyàn ń wá ọ̀nà láti pa á.
48 kintu tadupadēśē sarvvē lōkā niviṣṭacittāḥ sthitāstasmāt tē tatkarttuṁ nāvakāśaṁ prāpuḥ|
Wọn kò sì rí nǹkan kan tí wọn ìbá ṣe; nítorí gbogbo ènìyàn ṣù mọ́ ọn láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.

< lūkaḥ 19 >