< lūkaḥ 18 >

1 aparañca lokairaklāntai rnirantaraṁ prārthayitavyam ityāśayena yīśunā dṛṣṭānta ekaḥ kathitaḥ|
Ó sì pa òwe kan fún wọn láti fi yé wọn pe, ó yẹ kí a máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí a má sì ṣàárẹ̀.
2 kutracinnagare kaścit prāḍvivāka āsīt sa īśvarānnābibhet mānuṣāṁśca nāmanyata|
Wí pé, “Onídàájọ́ kan wà ní ìlú kan, tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn.
3 atha tatpuravāsinī kācidvidhavā tatsamīpametya vivādinā saha mama vivādaṁ pariṣkurvviti nivedayāmāsa|
Opó kan sì wà ní ìlú náà, ó sì ń tọ̀ ọ́ wá, wí pé, ‘Gbẹ̀san mi lára ọ̀tá mi!’
4 tataḥ sa prāḍvivākaḥ kiyaddināni na tadaṅgīkṛtavān paścāccitte cintayāmāsa, yadyapīśvarānna bibhemi manuṣyānapi na manye
“Lákọ̀ọ́kọ́ kò dá a lóhùn, ṣùgbọ́n níkẹyìn ó wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Bí èmi kò tilẹ̀ bẹ̀rù Ọlọ́run, tí èmi kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn,
5 tathāpyeṣā vidhavā māṁ kliśnāti tasmādasyā vivādaṁ pariṣkariṣyāmi nocet sā sadāgatya māṁ vyagraṁ kariṣyati|
Ṣùgbọ́n nítorí tí opó yìí ń yọ mí lẹ́nu, èmi ó gbẹ̀san rẹ̀, kí ó má ba à fi wíwá rẹ̀ nígbàkígbà dá mi lágara.’”
6 paścāt prabhuravadad asāvanyāyaprāḍvivāko yadāha tatra mano nidhadhvaṁ|
Olúwa sì wí pé, “Ẹ gbọ́ bí aláìṣòótọ́ onídàájọ́ ti wí!
7 īśvarasya ye 'bhirucitalokā divāniśaṁ prārthayante sa bahudināni vilambyāpi teṣāṁ vivādān kiṁ na pariṣkariṣyati?
Ọlọ́run kì yóò ha sì gbẹ̀san àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, tí ń fi ọ̀sán àti òru kígbe pè é, tí ó sì mú sùúrù fún wọn?
8 yuṣmānahaṁ vadāmi tvarayā pariṣkariṣyati, kintu yadā manuṣyaputra āgamiṣyati tadā pṛthivyāṁ kimīdṛśaṁ viśvāsaṁ prāpsyati?
Mo wí fún yín, yóò gbẹ̀san wọn kánkán! Ṣùgbọ́n nígbà tí Ọmọ Ènìyàn bá dé yóò ha rí ìgbàgbọ́ ní ayé bí?”
9 ye svān dhārmmikān jñātvā parān tucchīkurvvanti etādṛgbhyaḥ, kiyadbhya imaṁ dṛṣṭāntaṁ kathayāmāsa|
Ó sì pa òwe yìí fún àwọn kan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ara wọn pé, àwọn ni olódodo, tí wọ́n sì ń gan àwọn ẹlòmíràn,
10 ekaḥ phirūśyaparaḥ karasañcāyī dvāvimau prārthayituṁ mandiraṁ gatau|
pé, “Àwọn ọkùnrin méjì gòkè lọ sí tẹmpili láti gbàdúrà, ọ̀kan jẹ́ Farisi, èkejì sì jẹ́ agbowó òde.
11 tato'sau phirūśyekapārśve tiṣṭhan he īśvara ahamanyalokavat loṭhayitānyāyī pāradārikaśca na bhavāmi asya karasañcāyinastulyaśca na, tasmāttvāṁ dhanyaṁ vadāmi|
Èyí Farisi dìde, ó sì ń gbàdúrà nínú ara rẹ̀ báyìí pé, ‘Ọlọ́run mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí èmi kò rí bí àwọn ará ìyókù, àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà, aláìṣòótọ́, panṣágà, tàbí bí agbowó òde yìí.
12 saptasu dineṣu dinadvayamupavasāmi sarvvasampatte rdaśamāṁśaṁ dadāmi ca, etatkathāṁ kathayan prārthayāmāsa|
Èmi ń gbààwẹ̀ lẹ́ẹ̀méjì ní ọ̀sẹ̀, mo ń san ìdámẹ́wàá ohun gbogbo tí mo ní.’
13 kintu sa karasañcāyi dūre tiṣṭhan svargaṁ draṣṭuṁ necchan vakṣasi karāghātaṁ kurvvan he īśvara pāpiṣṭhaṁ māṁ dayasva, itthaṁ prārthayāmāsa|
“Ṣùgbọ́n agbowó òde dúró lókèèrè, kò tilẹ̀ jẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run, ṣùgbọ́n ó lu ara rẹ̀ ní oókan àyà, ó wí pé, ‘Ọlọ́run ṣàánú fún mi, èmi ẹlẹ́ṣẹ̀!’
14 yuṣmānahaṁ vadāmi, tayordvayo rmadhye kevalaḥ karasañcāyī puṇyavattvena gaṇito nijagṛhaṁ jagāma, yato yaḥ kaścit svamunnamayati sa nāmayiṣyate kintu yaḥ kaścit svaṁ namayati sa unnamayiṣyate|
“Mo wí fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀ ní ìdáláre ju èkejì lọ: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, òun ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹni tí ó bá sì rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ òun ni a ó gbéga.”
15 atha śiśūnāṁ gātrasparśārthaṁ lokāstān tasya samīpamāninyuḥ śiṣyāstad dṛṣṭvānetṛn tarjayāmāsuḥ,
Wọ́n sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn; ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí i, wọ́n ń bá wọn wí.
16 kintu yīśustānāhūya jagāda, mannikaṭam āgantuṁ śiśūn anujānīdhvaṁ tāṁśca mā vārayata; yata īśvararājyādhikāriṇa eṣāṁ sadṛśāḥ|
Ṣùgbọ́n Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọ kékeré wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má sì ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí tí irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
17 ahaṁ yuṣmān yathārthaṁ vadāmi, yo janaḥ śiśoḥ sadṛśo bhūtvā īśvararājyaṁ na gṛhlāti sa kenāpi prakāreṇa tat praveṣṭuṁ na śaknoti|
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gbà ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò wọ inú rẹ̀ bí ó ti wù kí ó rí.”
18 aparam ekodhipatistaṁ papraccha, he paramaguro, anantāyuṣaḥ prāptaye mayā kiṁ karttavyaṁ? (aiōnios g166)
Ìjòyè kan sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, wí pé, “Olùkọ́ rere, kín ni èmi ó ṣe tí èmi ó fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
19 yīśuruvāca, māṁ kutaḥ paramaṁ vadasi? īśvaraṁ vinā kopi paramo na bhavati|
Jesu wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí bí kò ṣe ẹnìkan, èyí sì ni Ọlọ́run.
20 paradārān mā gaccha, naraṁ mā jahi, mā coraya, mithyāsākṣyaṁ mā dehi, mātaraṁ pitarañca saṁmanyasva, etā yā ājñāḥ santi tāstvaṁ jānāsi|
Ìwọ mọ̀ àwọn òfin: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jẹ́rìí èké, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
21 tadā sa uvāca, bālyakālāt sarvvā etā ācarāmi|
Ó sì wí pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti pamọ́ láti ìgbà èwe mi wá.”
22 iti kathāṁ śrutvā yīśustamavadat, tathāpi tavaikaṁ karmma nyūnamāste, nijaṁ sarvvasvaṁ vikrīya daridrebhyo vitara, tasmāt svarge dhanaṁ prāpsyasi; tata āgatya mamānugāmī bhava|
Nígbà tí Jesu sì gbọ́ èyí, ó wí fún un pé, “Ohun kan ni ó kù fún ọ síbẹ̀: lọ ta ohun gbogbo tí o ní, kí o sì pín in fún àwọn tálákà, ìwọ ó sì ní ìṣúra ní ọ̀run: sì wá, kí o máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
23 kintvetāṁ kathāṁ śrutvā sodhipatiḥ śuśoca, yatastasya bahudhanamāsīt|
Nígbà tí ó sì gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, nítorí tí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
24 tadā yīśustamatiśokānvitaṁ dṛṣṭvā jagāda, dhanavatām īśvararājyapraveśaḥ kīdṛg duṣkaraḥ|
Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!
25 īśvararājye dhaninaḥ praveśāt sūceśchidreṇa mahāṅgasya gamanāgamane sukare|
Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
26 śrotāraḥ papracchustarhi kena paritrāṇaṁ prāpsyate?
Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
27 sa uktavān, yan mānuṣeṇāśakyaṁ tad īśvareṇa śakyaṁ|
Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
28 tadā pitara uvāca, paśya vayaṁ sarvvasvaṁ parityajya tava paścādgāmino'bhavāma|
Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
29 tataḥ sa uvāca, yuṣmānahaṁ yathārthaṁ vadāmi, īśvararājyārthaṁ gṛhaṁ pitarau bhrātṛgaṇaṁ jāyāṁ santānāṁśca tyaktavā
Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run,
30 iha kāle tato'dhikaṁ parakāle 'nantāyuśca na prāpsyati loka īdṛśaḥ kopi nāsti| (aiōn g165, aiōnios g166)
tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
31 anantaraṁ sa dvādaśaśiṣyānāhūya babhāṣe, paśyata vayaṁ yirūśālamnagaraṁ yāmaḥ, tasmāt manuṣyaputre bhaviṣyadvādibhiruktaṁ yadasti tadanurūpaṁ taṁ prati ghaṭiṣyate;
Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
32 vastutastu so'nyadeśīyānāṁ hasteṣu samarpayiṣyate, te tamupahasiṣyanti, anyāyamācariṣyanti tadvapuṣi niṣṭhīvaṁ nikṣepsyanti, kaśābhiḥ prahṛtya taṁ haniṣyanti ca,
Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára.
33 kintu tṛtīyadine sa śmaśānād utthāsyati|
Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
34 etasyāḥ kathāyā abhiprāyaṁ kiñcidapi te boddhuṁ na śekuḥ teṣāṁ nikaṭe'spaṣṭatavāt tasyaitāsāṁ kathānām āśayaṁ te jñātuṁ na śekuśca|
Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn, ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
35 atha tasmin yirīhoḥ purasyāntikaṁ prāpte kaścidandhaḥ pathaḥ pārśva upaviśya bhikṣām akarot
Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe.
36 sa lokasamūhasya gamanaśabdaṁ śrutvā tatkāraṇaṁ pṛṣṭavān|
Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí.
37 nāsaratīyayīśuryātīti lokairukte sa uccairvaktumārebhe,
Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
38 he dāyūdaḥ santāna yīśo māṁ dayasva|
Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
39 tatogragāminastaṁ maunī tiṣṭheti tarjayāmāsuḥ kintu sa punāruvan uvāca, he dāyūdaḥ santāna māṁ dayasva|
Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
40 tadā yīśuḥ sthagito bhūtvā svāntike tamānetum ādideśa|
Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í
41 tataḥ sa tasyāntikam āgamat, tadā sa taṁ papraccha, tvaṁ kimicchasi? tvadarthamahaṁ kiṁ kariṣyāmi? sa uktavān, he prabho'haṁ draṣṭuṁ labhai|
wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?” Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
42 tadā yīśuruvāca, dṛṣṭiśaktiṁ gṛhāṇa tava pratyayastvāṁ svasthaṁ kṛtavān|
Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
43 tatastatkṣaṇāt tasya cakṣuṣī prasanne; tasmāt sa īśvaraṁ dhanyaṁ vadan tatpaścād yayau, tadālokya sarvve lokā īśvaraṁ praśaṁsitum ārebhire|
Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.

< lūkaḥ 18 >