< Luka 20 >

1 Mar popur, učitelji dă zakonu alu Mojsije šă alci vođur kari as re židovur ur vinjit la Isus ăm una ză kănd ănvăca pă lumi ăm Hram šă propovjedale Hir fălos.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn ní tẹmpili tí ó sì ń wàásù ìyìnrere, àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà dìde sí i.
2 Jej lor ăntribat pă jăl: “Pă alu šinji autoritet fašj stvarurlješće? Šinji cu dat asta autoritet?”
Wọ́n sì wí fún un pé, “Sọ fún wa, àṣẹ wo ni ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Tàbí ta ni ó fún ọ ní àṣẹ yìí?”
3 Jăl u zăs: “Lasăcămă pă minji să vă ăntreb una stvar šă ăj dă voj să ăm ănturšjec vorba:
Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi pẹ̀lú yóò sì bi yín léèrè ọ̀rọ̀ kan; ẹ sì fi ìdáhùn fún mi.
4 Anume Dimizov u zăs alu Ivan să bučuzaskă pă ominj, ili ominji u zăs aje să fakă?”
Ìtẹ̀bọmi Johanu, láti ọ̀run wá ni tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn?”
5 Jej ur svătit una ku alt šă zăšje: “Dăkă anj zăšji ‘dă la Dimizov’, u ăntriba: ‘Adăšje atunšje nu ănkriđec?’
Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé, ‘Láti ọ̀run wá ni,’ òun yóò wí pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’
6 Ali dăkă anj zăšji noj: ‘Dă la ominj’, totă lume u vărlji petri pă noj să nji amori. Kă jej ăs uvjerilic kă Ivan are prorok.”
Ṣùgbọ́n bí àwa bá sì wí pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn,’ gbogbo ènìyàn ni yóò sọ wá ní òkúta, nítorí wọ́n gbàgbọ́ pé, wòlíì ni Johanu.”
7 Aša jej u ăntors vorba kă jej nu šćije dă hunđi u vinjit autoritet să bučuzaskă.
Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa kò mọ̀ ibi tí ó ti wá.”
8 Šă Isus u zăs: “Njiš ju nu vuj spunji ku alu šinji autoritet fak stvarurlješće.”
Jesu sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ èmi kì yóò wí fún yín àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
9 Isus su apukat să spujă usporedbă alu lume: “Are unu om kari u sămănat vinograd šă u lăsat ăm najam vinogradu alu šjeva ka ominji, šă jăl atunšje u fužjit dăm pămăntula pă maj lungă vremi.
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ sí í pa òwe yìí fún àwọn ènìyàn pé, “Ọkùnrin kan gbin ọgbà àjàrà kan, ó sì fi ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn olùṣọ́gbà, ó sì lọ sí àjò fún ìgbà pípẹ́.
10 Kănd u vinjit vreme, jăl u mănat pă sluga la ominj ăm vinograd să ăj đe parće aluj dăm plodur kari jej duguvule aluj, ali ominji lor bătut šă lor mănat ku mănjilje golji.
Nígbà tí ó sì tó àkókò, ó rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ kan sí àwọn olùṣọ́gbà náà, kí wọn lè fún un nínú èso ọgbà àjàrà náà, ṣùgbọ́n àwọn alágbàtọ́jú lù ú, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
11 Atunšje u mănat pă altu sluga ali šă pă jăl lor bătut, vređălit šă lor mănat ku mănjilje golji.
Ó sì tún rán ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn, wọ́n sì lù ú pẹ̀lú, wọ́n sì jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
12 Jăl u ănšjirkat să măji pă treći sluga, ali šă pă jăl lor ranalit šă lor arukănt.
Ó sì tún rán ẹ̀kẹta: wọ́n sì sá a lọ́gbẹ́ pẹ̀lú, wọ́n sì tì í jáde.
13 Gazda dă vinograd u zăs pă aje: ‘Šje să fak? Ju uj măna pă fišjoru amnjov plăkut. Dar kănd lu viđe pă jăl, pălăngă jăl ur ave respekt.’
“Nígbà náà ni Olúwa ọgbà àjàrà wí pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Èmi ó rán ọmọ mi àyànfẹ́ lọ: bóyá nígbà tí wọ́n bá rí i, wọn yóò bu ọlá fún un.’
14 Ali ominjije kănd lor văzut sur ligizit ăntri jej: ‘Jăl ăj nasljednik. Hajc să ăl amurănj aša nasljedstva aluj să nji rămăji anovă.’
“Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn alágbàtọ́jú náà rí i, wọ́n bá ara wọn gbèrò pé, ‘Èyí ni àrólé; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí ogún rẹ̀ lè jẹ́ ti wa.’
15 Atunšje lor dus afară dăm vinograd šă lor amurăt. Aku šje u fašji gazda dă vinograd?
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tì í jáde sẹ́yìn ọgbà àjàrà, wọ́n sì pa á. “Ǹjẹ́ kín ni olúwa ọgbà àjàrà náà yóò ṣe sí wọn?
16 Jăl u vinji šă u uništili pă ominjije. Šă u da ăm najam vinogradu alu alci.” Kănd u auzăt jej aje kum ominji urăt să ponašalešči, jej ur zăs: “Nu đe Dimizov!”
Yóò wá, yóò sì pa àwọn alágbàtọ́jú náà run, yóò sì fi ọgbà àjàrà náà fún àwọn ẹlòmíràn.” Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n ní, “Kí a má ri i!”
17 Jăl su ujtat pă jej, šă u zăs: “Skris ăj svăntă kenvija: ‘Petră kari graditelji u vărljit ăndărăt u fost aku petră zaglavnă?’ Šje značalešći asta?
Nígbà tí ó sì wò wọ́n, ó ní, “Èwo ha ni èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé’?
18 Toc kari kađi pă petre u fi zdrubit pă dărăbelji, šă toc pă kari kađi u fi zdrubic.”
Ẹnikẹ́ni tí ó ṣubú lu òkúta náà yóò fọ́; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí òun bá ṣubú lù, yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
19 Učitelji dă zakonu alu Mojsije šă mar popur ur ănšjirkat să pujă mănjilje pă jăl ăm ala šas ali alor lji frikă dă lumi. Jej ur prišjiput kă jăl u spus dă asta usporedbă protiv dă jej.
Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà láti mú un ní wákàtí náà; ṣùgbọ́n wọ́n bẹ̀rù àwọn ènìyàn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé, ó pa òwe yìí mọ́ wọn.
20 Popi šă alci vođur ăl pratale pă Isus šă or mănat pă špijunj, ominj kari trišje ka ominj đirepc kari ar trăbuji să ăl optužulaskă pă Isus ăm šjeva šje ar zăšji krivo aša să ăl adukă pă Isus ăm mănjilje dă upravitelj alu Rim.
Wọ́n sì ń ṣọ́ ọ, wọ́n sì rán àwọn ayọ́lẹ̀wò tí wọ́n ṣe ara wọn bí ẹni pé olóòtítọ́ ènìyàn, kí wọn ba à lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, kí wọn ba à lè fi í lé agbára àti àṣẹ Baálẹ̀ lọ́wọ́.
21 Aša lor ăntribat pă jăl: “Učitelju, noj ščijenj kă aje šje zăšj šă ănvec ăj točno, šă kă nu arec njiš šefălj parći, ali tu ănvacă anume kalje lu Dimizov.
Wọ́n sì bí i, pé, “Olùkọ́ àwa mọ̀ pé, ìwọ a máa sọ̀rọ̀ fún ni, ìwọ a sì máa kọ́ni bí ó ti tọ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ẹnìkan ṣùgbọ́n ìwọ ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run lóòtítọ́.
22 Aku ăj benji dă noj židovur să plăčenj porez lu car ili nu?”
Ǹjẹ́ ó tọ́ fún wa láti máa san owó òde fún Kesari, tàbí kò tọ́?”
23 Isus u shvatalit kum jej as re lukavi šă lju zăs alor:
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi àrékérekè wọn, ó sì wí fún wọn pé,
24 “Arătam banji ku kari plăčešč porezu. Aku alu šjinji ăj ubrazu šă numilje sus?” Jej ur zăs: “Alu car.”
“Ẹ fi owó idẹ kan hàn mí. Àwòrán àti àkọlé ti ta ni ó wà níbẹ̀?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ti Kesari ni.”
25 “Atunšje plăčec alu car šje ăj pripadalešći lu car šă dăđec lu Dimizov šje pripadalešći alu Dimizov!”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ fi ohun tí i ṣe ti Kesari fún Kesari, àti ohun tí í ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
26 Jej nu puće să aflji njimika rov ăm svatu aluj ăntri toc lumi, šă jej asre ămirac la ănturšjala dă vorba aluj, šă u tăkut.
Wọn kò sì lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú níwájú àwọn ènìyàn: ẹnu sì yà wọ́n sí ìdáhùn rẹ̀, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́.
27 Aku orikic saduceji kari zăšji kă njime nu su skula dăm morc ur vinjit la jăl, ku trik ăntribală:
Àwọn Sadusi kan sì tọ̀ ọ́ wá, àwọn tí wọ́n ń wí pé àjíǹde òkú kò sí wọ́n sì bi í,
28 Jej ur zăs: “Učitelju, Mojsije u pus žos zakon păntru noj kă dakă fračisu omuluj ar muri šă lasă pă băšăcaš făr dă kupij, atunšje fračisu aluj trăbă să u ămirići šă să răđišji familija păntru fračisu mort.
wí pé, “Olùkọ́, Mose kọ̀wé fún wa pé, Bí arákùnrin ẹnìkan bá kú, ní àìlọ́mọ, tí ó sì ní aya, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó lè gbé irú-ọmọ dìde fún arákùnrin rẹ̀.
29 Undată asre šapči frac. Elši u lot băšăcă šă u murit făr dă kupij.
Ǹjẹ́ àwọn arákùnrin méje kan ti wà; èkínní gbé ìyàwó, ó sì kú ní àìlọ́mọ.
30 Šă drugi u lotu pă je, šă jăl u murit făr dă kupij.
Èkejì sì ṣú u lópó: òun sì kú ní àìlọ́mọ.
31 Šă treći u lotu pă je. Maj toc šapči ur lotu šă ur murit, šă njiš unu no avut kupij ku je.
Ẹ̀kẹta sì ṣú u lópó: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn méjèèje pẹ̀lú: wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀, wọ́n sì kú.
32 Pă zadnji šă mujere u murit.
Nígbẹ̀yìn pátápátá obìnrin náà kú pẹ̀lú.
33 Aku lu šjinji u fi băšăce kănd or uskrsnuli morci? Ăngănđeščići kă toc šapči ur avutu dă băšăcă.”
Ǹjẹ́ ní àjíǹde òkú, aya ti ta ni yóò ha ṣe nínú wọn? Nítorí àwọn méjèèje ni ó sá à ni í ní aya.”
34 Isus u ăntors vorba alor: “Ăm asta svet lume să ămirită šă să ănsoră. (aiōn g165)
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Àwọn ọmọ ayé yìí a máa gbéyàwó, wọn a sì máa fa ìyàwó fún ni. (aiōn g165)
35 Ali eje kari ur fost smatralic vredni să uskrsnulaskă dăm morc njiš nu su ănsura, njiš nu să ămirită. (aiōn g165)
Ṣùgbọ́n àwọn tí a kà yẹ láti jogún ìyè ayérayé náà, àti àjíǹde kúrò nínú òkú, wọn kì í gbéyàwó, wọn kì í sì í fa ìyàwó fún ni. (aiōn g165)
36 Šă jej nu poći maj mult nikad să mori, kă jej ăs kupiji alu Dimizov daje kă ăs riđikac dăm morc. Jej ăs ka anđeji.
Nítorí wọn kò lè kú mọ́; nítorí tí wọn bá àwọn angẹli dọ́gba; àwọn ọmọ Ọlọ́run sì ni wọ́n, nítorí wọ́n di àwọn ọmọ àjíǹde.
37 Atunšje dă uskrsnuće šă Mojsije u arătat aje ăm svedočulala aluj dă grmu šje arđe. Akulo jăl čamă pă Domnu alu Dimizovu lu Abraham, Dimizovu lu Izak, šă Dimizovu lu Jakov, multă dobă dă pă šje jej ur murit.
Ní ti pé a ń jí àwọn òkú dìde, Mose tìkára rẹ̀ sì ti fihàn nínú igbó, nígbà tí ó pe ‘Olúwa ni Ọlọ́run Abrahamu, àti Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’
38 Anume, Dimizov nuj Dimizovu alu hej morc, mar alu hej kari kustă, kănd toc kustă păntru jăl.”
Bẹ́ẹ̀ ni òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, bí kò ṣe ti àwọn alààyè, nítorí gbogbo wọn wà láààyè fún un.”
39 Šjeva ka učitelji dă zakonu alu Mojsije u priznalit: “Učitelju, tu aj svitit benji!”
Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé dá a lóhùn, pé, “Olùkọ́ ìwọ wí rere!”
40 Dă pă aje jej nu sor maj ăndurat să ăl ănšjeršji ku ăntribalur.
Wọn kò sì jẹ́ bi í léèrè ọ̀rọ̀ kan mọ́.
41 Isus u ăntribat: “Šje gănđešći jej kum svitešći dă Mesija kă ăj numa Fišjoru lu Car David?
Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí wọ́n fi ń wí pé, ọmọ Dafidi ni Kristi?
42 David dă jăl săngur ăm kenvije dă Psalmur zăšji: ‘Domnu u zăs alu Domnu amnjov: Šăz pă desna parće ame.
Dafidi tìkára rẹ̀ sì wí nínú ìwé Saamu pé: “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
43 Šă ju uj vărlji pă dužmanji atej dăsup pišjorilje atelji.’
títí èmi ó fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”’
44 David jasno ăl čamă: ‘Domnu’, atunšje kum poći jăl să ăj fijă fišjor?”
Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ní ‘Olúwa.’ Òun ha sì ti ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
45 Isus svite lu učenici aluj a totă lume punje ureći.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní etí gbogbo ènìyàn pé,
46 Jăl u zăs: “Je sama dă učitelji dă zakon alu Mojsije. Jej uživalešči să să šetalaskă ăm haljinur lunž šă să fijă pozdravalic ku poštovanje ăm varuš pă trgur šă jej plašji să šadă lokurlje časni ăm sinagogur šă pă nuntur.
“Ẹ máa kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn akọ̀wé, tí wọ́n fẹ́ láti máa rìn nínú aṣọ gígùn, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọjà, àti ibùjókòó ọlá nínú Sinagọgu, àti ipò ọlá ní ibi àsè;
47 Jej pljačkalešći pă udovicur ăm kăšălje alor, kănd fašji lunž aruguminći dă predstavă. Ali jej ur kăpăta maj gre kaznă.”
Àwọn tí ó jẹ ilé àwọn opó run, tí wọ́n sì ń gbàdúrà gígùn fún àṣehàn, àwọn wọ̀nyí náà ni yóò jẹ̀bi pọ̀jù.”

< Luka 20 >