< Salmos 105 >

1 Agradecei ao SENHOR, chamai o seu nome; anunciai suas obras entre os povos.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Cantai a ele, tocai músicas para ele; falai de todas as suas maravilhas.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Tende orgulho de seu santo nome; alegre-se o coração dos que buscam ao SENHOR.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Buscai ao SENHOR e à sua força; buscai a presença dele continuamente.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Lembrai-vos de suas maravilhas, que ele fez; de seus milagres, e dos juízos de sua boca.
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Vós, [que sois da] semente de seu servo Abraão; vós, filhos de Jacó, seus escolhidos.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Ele é o SENHOR, nosso Deus; seus juízos [estão] em toda a terra.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Ele se lembra para sempre de seu pacto, da palavra que ele mandou até mil gerações;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 O qual ele firmou com Abraão, e de seu juramento a Isaque.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 O qual também confirmou a Jacó como estatuto, a Israel como pacto eterno.
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Dizendo: A ti darei a terra de Canaã, a porção de vossa herança.
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Sendo eles poucos em número; [eram] poucos, e estrangeiros nela.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 E andaram de nação em nação, de um reino a outro povo.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Ele não permitiu a ninguém que os oprimisse; e por causa deles repreendeu a reis,
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 [Dizendo]: Não toqueis nos meus ungidos, e não façais mal a meus profetas.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 E chamou a fome sobre a terra; ele interrompeu toda fonte de alimento;
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Enviou um homem adiante deles: José, [que] foi vendido como escravo.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Amarraram seus pés em correntes; ele foi preso com ferros;
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Até o tempo que sua mensagem chegou, a palavra do SENHOR provou o valor que ele tinha.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 O rei mandou que ele fosse solto; o governante de povos o libertou.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Ele o pôs como senhor de sua casa, e por chefe de todos os seus bens,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Para dar ordens a suas autoridades, e instruir a seus anciãos.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Então Israel entrou no Egito; Jacó peregrinou na terra de Cam.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 E fez seu povo crescer muito, e o fez mais poderoso que seus adversários.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 E mudou o coração [dos outros], para que odiassem ao seu povo, para que tratassem mal a seus servos.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 [Então] enviou seu servo Moisés, e a Arão, a quem tinha escolhido;
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 [Que] fizeram entre eles os sinais anunciados, e coisas sobrenaturais na terra de Cam.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Ele mandou trevas, e fez escurecer; e não foram rebeldes a sua palavra.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Ele transformou suas águas em sangue, e matou a seus peixes.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 A terra deles produziu rãs em abundância, [até] nos quartos de seus reis.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Ele falou, e vieram vários bichos [e] piolhos em todos os seus limites.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Tornou suas chuvas em saraiva; [pôs] fogo ardente em sua terra.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 E feriu suas vinhas e seus figueirais; e quebrou as árvores de seus territórios.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Ele falou, e vieram gafanhotos, e incontáveis pulgões;
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 E comeram toda a erva de sua terra; e devoraram o fruto de seus campos.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Também feriu a todos os primogênitos em sua terra; os primeiros de todas as suas forças.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 E os tirou [dali] com prata e ouro; e dentre suas tribos não houve quem tropeçasse.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 [Até] o Egito se alegrou com a saída deles, porque seu temor tinha caído sobre eles.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Ele estendeu uma nuvem como cobertor, e um fogo para iluminar a noite.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Eles pediram, e fez vir codornizes; e os fartou com pão do céu.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Ele abriu uma rocha, e dela saíram águas; [e] correram [como] um rio pelos lugares secos;
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Porque se lembrou de sua santa palavra, e de seu servo Abraão.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Então ele tirou [dali] a seu povo com alegria; e seus eleitos com celebração.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 E lhes deu as terras das nações; e do trabalho das nações tomaram posse;
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 Para que guardassem seus estatutos, e obedecessem a leis dele. Aleluia!
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Salmos 105 >