< Zachariasza 2 >

1 Potem [znowu] podniosłem swoje oczy i spojrzałem, a oto mężczyzna, w którego ręce był sznur mierniczy.
Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
2 I zapytałem: Dokąd idziesz? Odpowiedział mi: [Idę] zmierzyć Jerozolimę, by zobaczyć, jaka [jest] jej szerokość i jaka jej długość.
Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
3 A oto gdy Anioł, który rozmawiał ze mną, odchodził, inny anioł wyszedł mu naprzeciw.
Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
4 I powiedział do niego: Biegnij i powiedz temu młodzieńcowi: Jerozolima będzie zamieszkana jak miasta bez murów ze względu na mnóstwo ludu i bydła w niej.
Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
5 A ja, mówi PAN, będę dla niej murem ognistym dokoła i będę chwałą pośród niej.
Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
6 Hej, hej! Uciekajcie z ziemi północnej, mówi PAN, ponieważ rozproszyłem was na cztery strony świata, mówi PAN.
“Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
7 Ratuj się, o Syjonie, który mieszkasz u córki Babilonu.
“Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
8 Tak bowiem mówi PAN zastępów – posłał mnie na chwałę do tych narodów, które was ograbiły, bo kto was dotyka, dotyka źrenicy jego oka;
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
9 Oto podniosę swoją rękę przeciwko nim i staną się łupem dla swoich sług. I poznacie, że PAN zastępów mnie posłał.
Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
10 Zaśpiewaj i raduj się, córko Syjonu, bo oto przyjdę i zamieszkam pośród ciebie, mówi PAN.
“Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
11 Wiele narodów przyłączy się w tym dniu do PANA i będą moim ludem, a ja zamieszkam pośród ciebie i poznasz, że PAN zastępów posłał mnie do ciebie.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
12 Wtedy PAN weźmie Judę w posiadanie [jako] swój dział w ziemi świętej i znowu wybierze Jerozolimę.
Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
13 Niech umilknie wszelkie ciało przed PANEM. On bowiem powstał ze swego świętego przybytku.
Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”

< Zachariasza 2 >