< Psalmów 104 >

1 Błogosław, moja duszo, PANA. PANIE, mój Boże, jesteś bardzo wielki; odziałeś się w chwałę i majestat.
Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi. Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ; ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.
2 Okryłeś się światłością jak szatą, rozciągnąłeś niebiosa jak zasłonę.
Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ; ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní,
3 Zbudowałeś na wodach swoje komnaty, czynisz obłoki swym rydwanem, chodzisz na skrzydłach wiatru.
ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ. Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
4 Czynisz swoich aniołów duchami, swe sługi ogniem płonącym.
Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.
5 Założyłeś fundamenty ziemi, tak że się nigdy nie zachwieje.
O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀; tí a kò le è mì láéláé.
6 Okryłeś ją głębią jak szatą, wody stanęły nad górami.
Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ; àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.
7 Na twoje zgromienie rozbiegły się, a na głos twego grzmotu szybko pouciekały.
Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ, nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ.
8 Wzniosły się ponad góry, zniżyły się w doliny, na miejsce, które dla nich założyłeś.
wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀, sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.
9 Wyznaczyłeś [im] granicę, aby jej nie przekroczyły ani nie powróciły, by okryć ziemię.
Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀; láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
10 Wypuszczasz źródła po dolinach, [aby] płynęły między górami;
Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì; tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.
11 I napoiły wszystkie zwierzęta polne, dzikie osły gaszą [w nich] swoje pragnienie.
Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.
12 Przy nich mieszka ptactwo niebieskie i śpiewa pośród gałęzi.
Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.
13 Nawadniasz góry ze swoich komnat, owocami twoich dzieł syci się ziemia.
Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá; a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
14 Sprawiasz, że rośnie trawa dla bydła i zioła na użytek człowieka, żeby dobywał chleb z ziemi;
Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò, kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá.
15 I wino, które rozwesela serce człowieka, i oliwę, od której rozjaśnia się twarz, i chleb, który krzepi serce ludzkie.
Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀, òróró láti mú ojú rẹ̀ tan, àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.
16 Nasycone są drzewa PANA, cedry Libanu, które zasadził;
Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára, kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.
17 Na których ptaki mają swe gniazda; jedliny, na których bocian [ma] swój dom.
Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.
18 Wysokie góry są dla górskich kozłów, a skały [są] schronieniem dla królików.
Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó; àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.
19 Uczynił księżyc, aby odmierzał czas; słońce zna swój zachód.
Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.
20 Sprowadzasz ciemność i nastaje noc, w której wychodzą wszystkie zwierzęta leśne.
Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru, nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.
21 Lwiątka ryczą za łupem i szukają swego pokarmu od Boga.
Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
22 Słońce wstaje, schodzą się razem i kładą się w swoich jamach.
Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.
23 [Wtedy] wychodzi człowiek do swojej roboty i do swojej pracy aż do wieczora.
Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn, àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.
24 O, jak liczne są twoje dzieła, PANIE! Wszystkie je uczyniłeś mądrze, ziemia jest pełna twego bogactwa.
Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa! Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn: ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.
25 Oto morze wielkie i szerokie, w nim niezliczone istoty pełzające, zwierzęta małe i wielkie.
Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú, tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.
26 Po nim pływają okręty i Lewiatan, którego stworzyłeś, aby w nim igrał.
Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn, àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.
27 Wszystko to czeka na ciebie, abyś dał im pokarm we właściwym czasie.
Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́ láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.
28 [Gdy] dajesz im, zbierają; gdy otwierasz swą rękę, sycą się dobrami.
Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn, wọn yóò kó jọ; nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀, a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.
29 [Lecz gdy] ukrywasz swe oblicze, trwożą się; gdy odbierasz im ducha, giną i obracają się w proch.
Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́ ara kò rọ̀ wọ́n nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ, wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.
30 [Gdy] wysyłasz twego ducha, zostają stworzone i odnawiasz oblicze ziemi.
Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ, ni a dá wọn, ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.
31 Niech chwała PANA trwa na wieki, niech się raduje PAN swymi dziełami.
Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé; kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀,
32 Patrzy na ziemię, a ona drży, dotyka gór, a dymią.
ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì, ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.
33 Będę śpiewał PANU, póki żyję; będę śpiewał memu Bogu, póki istnieję.
Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa: èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.
34 Moje rozmyślanie o nim wdzięczne będzie, rozraduję się w PANU.
Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.
35 Niech zostaną wytraceni z ziemi grzesznicy i niech nie będzie już niegodziwych! Błogosław, moja duszo, PANA. Alleluja.
Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi. Yin Olúwa.

< Psalmów 104 >