< Nehemiasza 12 >

1 A oto kapłani i Lewici, którzy przybyli z Zorobabelem, synem Szealtiela, i z Jeszuą: Serajasz, Jeremiasz, Ezdrasz;
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
2 Amariasz, Malluk, Chattusz;
Amariah, Malluki, Hattusi,
3 Szekaniasz, Rechum, Meremot;
Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
4 Iddo, Ginneton, Abiasz;
Iddo, Ginetoni, Abijah,
5 Mijamin, Maadiasz, Bilga;
Mijamini, Moadiah, Bilgah,
6 Szemajasz, Jojarib, Jedajasz;
Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
7 Sallu, Amok, Chilkiasz, Jedajasz. To [byli] przedniejsi z kapłanów i ze swoich braci za dni Jeszuy.
Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
8 A Lewici: Jeszua, Binnuj, Kadmiel, Szerebiasz, Juda i Mattaniasz, który wraz z braćmi kierował śpiewem [pieśni dziękczynnych].
Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
9 A Bakbukiasz i Unni, ich bracia, [stali] naprzeciw nich w [swoich] służbach.
Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
10 Jeszua spłodził Jojakima, a Jojakim spłodził Eliasziba, a Eliaszib spłodził Jojadę;
Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
11 Jojada spłodził Jonatana, a Jonatan spłodził Jadduę.
Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
12 A za dni Jojakima naczelnikami rodu byli [następujący] kapłani: z Serajasza – Merajasz, z Jeremiasza – Chananiasz;
Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
13 Z Ezdrasza – Meszullam, z Amariasza – Jehochanan;
ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
14 Z Malluki – Jonatan, z Szebaniasza – Józef;
ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
15 Z Charima – Adna, z Merajota – Chelkaj;
ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
16 Z Iddo – Zachariasz, z Ginneto – Meszullam;
ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
17 Z Abiasza – Zikri, z Miniamina i Moadiasza – Piltaj;
ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
18 Z Bilgi – Szammua, z Szemajasza – Jonatan;
ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
19 A z Jojariba – Mattenaj, z Jedajasza – Uzzi;
ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
20 Z Sallaj – Kallaj, z Amoka – Eber;
ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
21 Z Chilkiasza – Chaszabiasz, z Jedajasza – Netanaeel.
ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
22 Za dni Eliasziba, Jojady, Jochanana i Jadduy Lewici zostali spisani jako naczelnicy rodów, a także kapłani, aż do panowania Dariusza Persa.
Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
23 Synowie Lewiego, naczelnicy rodów, [zostali] spisani w księdze kronik aż do dni Jochanana, syna Eliasziba.
Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
24 Naczelnikami Lewitów [byli]: Chaszabiasz, Szerebiasz, Jeszua, syn Kadmiela, i ich bracia, którzy stali naprzeciw nich, straż przy straży, aby chwalić i dziękować, według rozkazu Dawida, męża Bożego.
Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
25 Mattaniasz i Bakbukiasz, Obadiasz, Meszullam, Talmon i Akkub [jako] odźwierni trzymali straż przy składnicach u bram.
Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
26 Ci [żyli] za dni Jojakima, syna Jeszuy, syna Jocadaka, i za dni namiestnika Nehemiasza i Ezdrasza, kapłana i uczonego w Piśmie.
Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
27 I na poświęcanie muru Jerozolimy odszukano Lewitów ze wszystkich ich miejsc, aby ich przyprowadzić do Jerozolimy, by mogli obchodzić poświęcenie z radością, dziękczynieniem, przy śpiewaniu, cymbałach, cytrach i harfach.
Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
28 Zgromadzili się więc synowie śpiewaków, z równin wokół Jerozolimy i ze wsi Netofatytów;
A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
29 Także z domu Gilgal, z pól Geba i z Azmawet. Śpiewacy bowiem zbudowali sobie wsie wokół Jerozolimy.
láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
30 Wtedy kapłani i Lewici oczyścili się, po czym oczyścili też lud, bramy i mur.
Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
31 Następnie kazałem przełożonym Judy wstąpić na mur i ustawiłem dwa wielkie zespoły dziękczynne, z których [jeden] szedł po murze na prawo, w kierunku Bramy Gnojnej.
Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
32 Za nim szedł Hoszajasz i połowa przełożonych Judy;
Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
33 Także Azariasz, Ezdrasz i Meszullam;
àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
34 Juda, Beniamin, Szemajasz i Jeremiasz;
Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
35 Potem [szli] z trąbami niektórzy z synów kapłanów, [mianowicie]: Zachariasz, syn Jonatana, syna Szemajasza, syna Mattaniasza, syna Michajasza, syna Zakkura, syna Asafa;
pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
36 I jego bracia: Szemajasz, Azarel, Milalaj, Gilalaj, Maaj, Netaneel, Juda, Chanani z instrumentami muzycznymi Dawida, męża Bożego, a Ezdrasz, uczony w Piśmie, [szedł] przed nimi.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
37 Następnie przy Bramie Źródlanej, która [była] naprzeciw nich, szli po schodach miasta Dawida, które prowadzą na mur, znad domu Dawida aż do Bramy Wodnej na wschodzie.
Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
38 A drugi zespół dziękczynny, a ja za nim, szedł po murze w lewo z drugą połową [przełożonych], od Wieży Pieców aż do Muru Szerokiego;
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
39 I znad Bramy Efraima, nad Bramą Starą, nad Bramą Rybną, obok Wieży Chananeela i Wieży Mea, aż do Bramy Owczej. I stanęli u Bramy Więziennej.
kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
40 A tak stanęły oba zespoły dziękczynne w domu Bożym, a wraz z nimi ja i połowa przełożonych ze mną.
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
41 Także kapłani: Eliakim, Maasejasz, Miniamin, Michajasz, Elioenaj, Zachariasz, Chananiasz, z trąbami;
àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
42 I Maasejasz, Szemajasz, Eleazar, Uzzi, Jehochanan, Malkiasz, Elam i Ezer. Śpiewacy głośno śpiewali, a Jizrachiasz był [ich] kierownikiem.
Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
43 Tego dnia składali także wielkie ofiary i radowali się. Bóg bowiem dał im wielką radość. Również kobiety i dzieci radowały się, a radość Jerozolimy słychać było z daleka.
Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
44 W tym czasie ustanowiono mężczyzn nad składnicami dla skarbów, ofiar, pierwocin i dziesięcin, aby w nich zgromadzono dla kapłanów i Lewitów udziały przyznane im przez Prawo z pól miejskich. Juda bowiem cieszył się z powodu kapłanów i Lewitów pełniących służbę;
Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
45 I śpiewacy i odźwierni pełnili służbę dla swego Boga i służbę oczyszczenia, według rozkazu Dawida [i] jego syna Salomona.
Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
46 Już bowiem dawno, za dni Dawida i Asafa, [byli ustanowieni] przełożeni nad śpiewakami oraz [były ustalone] pieśni pochwalne i dziękczynienia dla Boga.
Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
47 Cały Izrael więc za dni Zorobabela i za dni Nehemiasza dawał porcje śpiewakom i odźwiernym na codzienne utrzymanie. Oddawali Lewitom to, co poświęcili, Lewici zaś oddawali [to] synom Aarona.
Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.

< Nehemiasza 12 >