< Jozuego 23 >

1 A po długim czasie, gdy PAN dał Izraelowi odpoczynek od wszystkich ich okolicznych wrogów, a Jozue był już stary i w podeszłym wieku;
Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
2 Jozue przywołał całego Izraela, jego starszych, jego naczelników, jego sędziów i jego przełożonych i powiedział do nich: Jestem już stary i w podeszłym wieku.
Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
3 A wy widzieliście wszystko, co PAN, wasz Bóg, uczynił wszystkim tym narodom ze względu na was, gdyż PAN, wasz Bóg, sam walczył za was.
Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
4 Spójrzcie, podzieliłem wam losem narody, które pozostały, jako dziedzictwo dla waszych pokoleń, i wszystkie narody, które wytraciłem, od Jordanu aż do Morza Wielkiego na zachodzie.
Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 A PAN, wasz Bóg, sam je wypędzi przed wami i wygna je sprzed waszych oczu, i posiądziecie dziedzicznie ich ziemię, jak wam to powiedział PAN, wasz Bóg.
Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
6 Umacniajcie się bardzo, by strzec i wypełniać wszystko, co jest napisane w księdze Prawa Mojżesza, nie odstępując od niego na prawo [ani] na lewo.
“Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
7 Nie mieszajcie się z tymi narodami, które pozostały pośród was, ani nie wspominajcie imion ich bogów, ani [na nich] nie przysięgajcie, ani im nie służcie, ani nie oddawajcie im pokłonu;
Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
8 Ale lgnijcie do PANA, swojego Boga, tak jak czyniliście aż do dziś.
Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
9 PAN bowiem wypędził przed wami narody wielkie i potężne i nikt nie mógł ostać się przed wami aż do dziś.
“Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
10 Jeden z was będzie ścigał tysiąc, gdyż PAN, wasz Bóg, sam walczy za was, jak wam obiecał.
Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
11 Strzeżcie się więc pilnie, byście miłowali PANA, waszego Boga.
Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
12 Jeśli bowiem odwrócicie się i przylgniecie do pozostałych narodów, do tych, które pozostały pośród was, i spowinowacicie się z nimi, i pomieszacie się z nimi, a one z wami;
“Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
13 To wiedzcie na pewno, że PAN, wasz Bóg, nie będzie więcej wyganiał tych narodów przed wami, ale będą dla was sidłem i pułapką, biczem na wasze boki i cierniem dla waszych oczu, aż wyginiecie z tej przewybornej ziemi, którą dał wam PAN, wasz Bóg.
Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
14 A oto idę dziś drogą całej ziemi; poznajcie więc z całego swojego serca i całą swoją duszą, że nie zawiodło żadne słowo ze wszystkich dobrych słów, które mówił o was PAN, wasz Bóg; wszystkie wam się wypełniły, a nie zawiodło żadne słowo.
“Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
15 Dlatego tak jak wam się wypełniło każde dobre słowo, które obiecał wam PAN, wasz Bóg, tak PAN sprowadzi na was każde złe słowo, aż was wytraci z tej przewybornej ziemi, którą wam dał PAN, wasz Bóg.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
16 Jeśli złamiecie przymierze PANA, swojego Boga, które wam przykazał, i pójdziecie służyć obcym bogom, i będziecie oddawać im pokłon, wtedy gniew PANA rozpali się przeciw wam i zginiecie prędko z tej przewybornej ziemi, którą wam dał.
Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”

< Jozuego 23 >