< Ezechiela 38 >

1 I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Synu człowieczy, zwróć swoją twarz przeciwko Gogowi w ziemi Magog, naczelnemu księciu w Meszek i Tubal, i prorokuj przeciw niemu.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
3 I mów: Tak mówi Pan BÓG: Oto jestem przeciw tobie, Gogu, naczelny księciu w Meszek i Tubal.
kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
4 Zawrócę cię i włożę haki w twoje szczęki, i wyprowadzę ciebie i całe twoje wojsko, konie i jeźdźców, wszystkich w pełnym uzbrojeniu, wielki zastęp z tarczami i puklerzami, wszystkich władających mieczem;
Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
5 A z nimi Persów, Etiopczyków i Putejczyków, wszystkich uzbrojonych w tarczę i hełm;
Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
6 Gomer i wszystkie jego oddziały, dom Togarmy z północnych stron i wszystkie jego oddziały, liczne narody z tobą.
Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
7 Przygotuj się i bądź gotowy, ty i twoje wszystkie zastępy, które się zebrały u ciebie, i bądź ich stróżem.
“‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
8 Po wielu dniach zostaniesz nawiedzony, przy końcu lat przybędziesz do ziemi uwolnionej od miecza, której [lud] został zebrany spośród wielu narodów, na góry Izraela, które były długo spustoszeniem, a będąc wyprowadzeni spośród narodów, oni wszyscy zamieszkają bezpiecznie.
Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
9 Wyruszysz i nadciągniesz jak burza, będziesz jak chmura okrywająca ziemię, ty i wszystkie twoje zastępy oraz liczne ludy z tobą.
Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
10 Tak mówi Pan BÓG: W tym dniu zrodzą się myśli w twoim sercu i będziesz miał złe zamiary;
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
11 I powiesz: Wyruszę do ziemi o nieobwarowanych wsiach; napadnę na [ludzi] spokojnych, którzy mieszkają bezpiecznie, na wszystkich, którzy mieszkają bez murów i nie mają ani rygli, ani bram;
Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
12 Aby zabrać łupy i zagarnąć zdobycze, aby swą rękę położyć na spustoszone miejsca, [które znowu] zostały zamieszkane, i na lud zgromadzony spośród narodów, który zdobył bydło i dobra, a mieszka w środku ziemi.
Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
13 Szeba, Dedan i kupcy Tarszisz oraz wszystkie jego lwięta zapytają cię: Czy przybyłeś, aby zabrać łupy? Czy na zagarnięcie zdobyczy zgromadziłeś swoje zastępy, aby zabrać srebro i złoto, zabierać bydło i dobra, aby zgarnąć wielki łup?
Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
14 Dlatego prorokuj, synu człowieczy, i mów do Goga: Tak mówi Pan BÓG: Czy w dniu, gdy mój lud Izraela będzie mieszkał bezpiecznie, nie będziesz [o tym] wiedział?
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
15 I przyjdziesz ze swego miejsca z północnych stron, ty i liczne ludy z tobą, wszyscy jadący na koniach, wielki zastęp i liczne wojsko;
Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
16 I nadciągniesz przeciwko mojemu ludowi Izraela jak chmura, by okryć tę ziemię. W dniach ostatecznych przyprowadzę cię do swojej ziemi, aby poznały mnie narody, gdy będę uświęcony w tobie, Gogu, na ich oczach.
Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
17 Tak mówi Pan BÓG: Czyż ty nie [jesteś] tym, o którym mówiłem w dawnych dniach przez moje sługi, proroków Izraela, którzy prorokowali za dni tamtych lat, że ja sprowadzę cię na nich?
“‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
18 Ale w dniu, w którym Gog nadciągnie przeciwko ziemi Izraela, mówi Pan BÓG, wzmoże się zapalczywość mego gniewu;
Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
19 Powiedziałem bowiem w swojej gorliwości i w ogniu swojego gniewu: Zaprawdę, w tym dniu będzie wielkie trzęsienie w ziemi Izraela;
Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
20 I zadrżą przede mną ryby morskie i ptactwo niebieskie, zwierzęta polne i wszelkie zwierzęta pełzające po ziemi, a także wszyscy ludzie, którzy są na powierzchni ziemi; rozpadną się góry, upadną wysokie wieże i każdy mur runie na ziemię.
Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
21 Przywołam miecz przeciwko niemu po wszystkich moich górach, mówi Pan BÓG. Miecz każdego zwróci się przeciwko swemu bratu.
Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
22 I osądzę go zarazą i krwią, ześlę ulewny deszcz i kamienie gradu, ogień i siarkę – na niego, na jego wojska i na liczne ludy, które z nim [będą].
Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
23 Okażę się wielki i święty i dam się poznać na oczach wielu narodów, i poznają, że ja jestem PANEM.
Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’

< Ezechiela 38 >