< Kaznodziei 9 >

1 Zaprawdę, wszystko to rozważałem w swoim sercu po to, aby to wszystko wyjaśnić – że sprawiedliwi i mądrzy oraz ich dzieła [są] w rękach Boga. Człowiek nie zna ani miłości, ani nienawiści ze wszystkich rzeczy, które są przed nim.
Nígbà náà ni mo wá ronú lórí gbogbo èyí, tí mo sì parí rẹ̀ pé, olóòtọ́ àti ọlọ́gbọ́n àti ohun tí wọ́n ń ṣe wà ní ọwọ́ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n kò sí ènìyàn tí ó mọ̀ bóyá ìfẹ́ tàbí ìríra ni ó ń dúró de òun.
2 Wszystkich [spotyka] to samo: ten sam los spotyka sprawiedliwego i niegodziwego, dobrego i czystego, i nieczystego, składającego ofiary i tego, który nie składa ofiar, zarówno dobrego, jak i grzesznika, przysięgającego i tego, kto boi się przysięgi.
Àyànmọ́ kan náà ni gbogbo wọn yàn—olóòtọ́ àti ènìyàn búburú, rere àti ibi, mímọ́ àti àìmọ́, àwọn tí ó ń rú ẹbọ àti àwọn tí kò rú ẹbọ. Bí ó ti rí pẹ̀lú ènìyàn rere bẹ́ẹ̀ náà ni ó rí pẹ̀lú ẹni tó dẹ́ṣẹ̀ bí ó ti rí pẹ̀lú àwọn tí ó ń ṣe ìbúra bẹ́ẹ̀ náà ni ó rí pẹ̀lú àwọn tí ó ń bẹ̀rù láti ṣe ìbúra.
3 Jest takie zło we wszystkim, co się dzieje pod słońcem: jeden los spotyka wszystkich. A przy tym serce synów ludzkich jest pełne zła, a głupota [znajduje się] w ich sercach, póki żyją, a potem [idą] do zmarłych.
Ohun búburú ni èyí jẹ́ nínú gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn. Ìpín kan ṣoṣo ni ó ń dúró de gbogbo wọn, ọkàn ènìyàn pẹ̀lú kún fún ibi, ìsínwín sì wà ní ọkàn wọn nígbà tí wọ́n wà láààyè àti nígbà tí wọ́n bá darapọ̀ mọ́ òkú.
4 Ktokolwiek bowiem jest złączony ze wszystkimi żyjącymi, ma nadzieję, gdyż lepszy jest żywy pies niż zdechły lew.
Ẹnikẹ́ni tí ó wà láàrín alààyè ní ìrètí—kódà ààyè ajá sàn dáradára ju òkú kìnnìún lọ!
5 Żyjący bowiem wiedzą, że umrą, ale umarli o niczym nie wiedzą i nie mają już żadnej zapłaty, gdyż pamięć o nich uległa zapomnieniu.
Nítorí pé ẹni tí ó wà láààyè mọ̀ wí pé àwọn yóò kú ṣùgbọ́n òkú kò mọ ohun kan wọn kò ní èrè kankan mọ́, àti pé kódà ìrántí wọn tí di ohun ìgbàgbé.
6 Tak samo ich miłość, nienawiść i zazdrość już zginęły. I już nigdy więcej nie będą mieć działu we wszystkim, co się dzieje pod słońcem.
Ìfẹ́ wọn, ìríra wọn, àti ìlara wọn ti parẹ́: láéláé kọ́ ni wọn yóò tún ní ìpín nínú ohunkóhun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn.
7 Idź więc, jedz z radością swój chleb i pij z wesołym sercem swe wino, gdyż Bóg już przyjął twoje dzieła.
Lọ jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ayọ̀, kí o sì mu ọtí wáìnì rẹ pẹ̀lú inú dídùn dé ọkàn, nítorí pé ìsinsin yìí ni Ọlọ́run síjú àánú wo ohun tí o ṣe.
8 Niech twoje szaty będą zawsze białe i niech nie zabraknie olejku na twoją głowę.
Máa wọ aṣọ funfun nígbàkígbà kí o sì máa fi òróró yan orí rẹ nígbà gbogbo.
9 Ciesz się życiem z żoną, którą ukochałeś po wszystkie dni swego marnego życia, jakie dał ci [Bóg] pod słońcem, po wszystkie dni swojej marności. To jest bowiem twój dział w życiu i w trudzie, który podejmujesz pod słońcem.
Máa jẹ ayé pẹ̀lú ìyàwó rẹ, ẹni tí o fẹ́ràn, ní gbogbo ọjọ́ ayé àìní ìtumọ̀ yí tí Ọlọ́run ti fi fún ọ lábẹ́ oòrùn—gbogbo ọjọ́ àìní ìtumọ̀ rẹ. Nítorí èyí ni ìpín tìrẹ ní ayé àti nínú iṣẹ́ wàhálà rẹ ní abẹ́ oòrùn.
10 Wszystko, cokolwiek twoja ręka postanowi czynić, czyń z całej swojej siły; [nie ma] bowiem żadnej pracy ani zamysłu, ani wiedzy, ani mądrości w grobie, do którego zmierzasz. (Sheol h7585)
Ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá rí láti ṣe, ṣe é pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ, nítorí kò sí iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ìpinnu tàbí ìmọ̀ tàbí ọgbọ́n nínú isà òkú níbi tí ò ń lọ. (Sheol h7585)
11 Potem obróciłem się i widziałem pod słońcem, że bieg nie [należy] do szybkich ani wojna do dzielnych, ani żywność do mądrych, ani bogactwo do roztropnych, ani łaska do zdolnych, lecz czas i przypadek spotyka wszystkich.
Mo ti rí ohun mìíràn lábẹ́ oòrùn. Eré ìje kì í ṣe fún ẹni tí ó yára tàbí ogun fún alágbára, bẹ́ẹ̀ ni oúnjẹ kò wà fún ọlọ́gbọ́n tàbí ọrọ̀ fún ẹni tí ó ní òye tàbí ojúrere fún ẹni tí ó ní ìmọ̀; ṣùgbọ́n ìgbà àti èsì ń ṣẹlẹ̀ sí gbogbo wọn.
12 Człowiek bowiem nie zna swojego czasu, ale jak ryby, które się łowi szkodliwą siecią, i jak ptaki chwytane w sidła, tak synowie ludzcy są uwikłani w złej chwili, gdy ta nagle na nich spadnie.
Síwájú sí i, kò sí ẹni tí ó mọ ìgbà tí àkókò rẹ̀ yóò dé, gẹ́gẹ́ bí a ti ń mú ẹja nínú àwọ̀n búburú tàbí tí a ń mú ẹyẹ nínú okùn gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni a ń mú ènìyàn ní àkókò ibi tí ó ṣubú lù wọ́n láìròtẹ́lẹ̀.
13 Widziałem również tę mądrość pod słońcem, która wydała mi się wielka:
Mo sì tún rí àpẹẹrẹ ọgbọ́n tí ó dùn mọ́ mi lábẹ́ oòrùn.
14 Było małe miasto, a w nim niewielu ludzi. I wyruszył przeciw niemu potężny król, obległ je i zbudował przeciwko niemu wielkie wały.
Ìlú kékeré kan tí ènìyàn díẹ̀ wà nínú rẹ̀ wà ní ìgbà kan rí. Ọba alágbára kan sì ṣígun tọ ìlú náà lọ, ó yí i po, ó sì kọ́ ilé ìṣọ́ tí ó tóbi lòdì sí i.
15 I znalazł się w nim człowiek ubogi i mądry, który wybawił to miasto przez swoją mądrość. Nikt jednak nie pamiętał tego ubogiego człowieka.
Ṣùgbọ́n, tálákà ọkùnrin tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n kan ń gbé ní ìlú náà, ó sì gba gbogbo ìlú u rẹ̀ là pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀. Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó rántí ọkùnrin tálákà náà.
16 I powiedziałem: Lepsza jest mądrość niż siła. Lecz mądrość ubogiego bywa wzgardzona i jego słów nikt nie słucha.
Nítorí náà mo sọ wí pé, “Ọgbọ́n dára ju agbára.” Ṣùgbọ́n a kẹ́gàn ọgbọ́n ọkùnrin tálákà náà, wọn kò sì mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe.
17 Spokojnych słów ludzi mądrych należy słuchać bardziej niż krzyku tego, który panuje wśród głupców.
Ọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa wà ní ìmúṣẹ ju igbe òmùgọ̀ alákòóso lọ.
18 Lepsza jest mądrość niż oręż wojenny, ale jeden grzesznik niszczy wiele dobrego.
Ọgbọ́n dára ju ohun èlò ogun lọ, ṣùgbọ́n ẹnìkan tó dẹ́ṣẹ̀ a máa ba ohun dídára púpọ̀ jẹ́.

< Kaznodziei 9 >