< Kaznodziei 1 >

1 Słowa Kaznodziei, syna Dawida, króla w Jerozolimie.
Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:
2 Marność nad marnościami – mówi Kaznodzieja – marność nad marnościami. Wszystko jest marnością.
“Asán inú asán!” Oníwàásù náà wí pé, “Asán inú asán! Gbogbo rẹ̀ asán ni.”
3 Jaki pożytek ma człowiek z całego swego trudu, który podejmuje pod słońcem?
Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?
4 Jedno pokolenie przemija, [drugie] pokolenie przychodzi, lecz ziemia trwa na wieki.
Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ, síbẹ̀ ayé dúró títí láé.
5 Słońce wschodzi i słońce zachodzi, i spieszy do swego miejsca, z którego znów wschodzi.
Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀, ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.
6 Wiatr idzie na południe i zawraca na północ, krąży nieustannie i znowu wraca na drogę swego krążenia.
Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù, Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá, a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.
7 Wszystkie rzeki płyną do morza, lecz morze się nie przepełnia; do miejsca, z którego rzeki płyną, [znowu] wracają.
Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun, síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún. Níbi tí àwọn odò ti wá, níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.
8 Wszystkie rzeczy [są] pełne trudu, a człowiek nie zdoła tego wyrazić. Oko nie nasyci się patrzeniem ani ucho nie napełni się słuchaniem.
Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá, ju èyí tí ẹnu le è sọ. Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn, bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.
9 To, co było, jest tym, co będzie; a to, co się stało, jest tym, co się stanie. I nie ma nic nowego pod słońcem.
Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn òun ni a ó tún máa ṣe padà kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.
10 Czy jest coś, o czym można by powiedzieć: Patrz, to jest coś nowego? I to już było w dawnych czasach, które były przed nami.
Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé, “Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”? Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́, o ti wà ṣáájú tiwa.
11 Nie ma pamięci o dawnych rzeczach; także o tych, które będą, nie będzie pamięci u tych, którzy potem nastaną.
Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀ lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.
12 Ja, Kaznodzieja, byłem królem nad Izraelem w Jerozolimie.
Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí.
13 I przyłożyłem się w swoim sercu [do tego], aby mądrością szukać wszystkiego i wybadać wszystko, co się dzieje pod niebem. To uciążliwe zadanie Bóg dał synom ludzkim, aby się nim trudzili.
Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn.
14 Widziałem wszystkie sprawy, jakie się dzieją pod słońcem, a oto wszystko jest marnością i utrapieniem ducha.
Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
15 Tego, co krzywe, nie da się wyprostować, a tego, czego brak, nie da się policzyć.
Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́, ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.
16 Tak więc pomyślałem w swoim sercu: Oto wzbogaciłem się i dano mi więcej mądrości niż wszystkim, którzy byli przede mną w Jerozolimie. I moje serce doświadczyło wielkiej mądrości i wiedzy.
Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.”
17 I przyłożyłem się w swoim sercu [do tego], aby poznać mądrość, a także by poznać szaleństwo i głupotę. [Ale] poznałem, że i to jest utrapieniem ducha.
Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
18 Gdzie bowiem jest wiele mądrości, [tam] jest wiele smutku. A kto przysparza wiedzy, przysparza i cierpienia.
Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá, bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.

< Kaznodziei 1 >