< II Królewska 21 >

1 Manasses miał dwanaście lat, kiedy zaczął królować, i królował pięćdziesiąt pięć lat w Jerozolimie. Jego matka miała na imię Chefsiba.
Manase jẹ́ ẹni ọdún méjìlá nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Hẹfisiba.
2 Czynił on to, co złe w oczach PANA, według obrzydliwości tych narodów, które PAN wypędził przed synami Izraela.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ó sì tẹ̀lé iṣẹ́ ìríra tí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
3 Odbudował bowiem wyżyny, które zburzył jego ojciec Ezechiasz, wznosił ołtarze dla Baala, posadził gaj, tak jak uczynił Achab, król Izraela, i oddawał pokłon całemu zastępowi nieba, i służył mu.
Ó sì tún ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah tí ó parun kọ́. Ó sì tún gbé pẹpẹ Baali dìde, ó sì ṣe ère òrìṣà Aṣerah, gẹ́gẹ́ bí Ahabu ọba Israẹli ti ṣe. Ó sì tẹríba sí gbogbo ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.
4 Zbudował też ołtarze w domu PANA, o którym PAN powiedział: W Jerozolimie umieszczę swoje imię.
Ó sì kọ́ pẹpẹ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ní Jerusalẹmu ni èmi yóò kọ orúkọ mi sí.”
5 Zbudował też ołtarze całemu zastępowi nieba w obydwu dziedzińcach domu PANA.
Ní àgbàlá méjèèjì ilé Olúwa, ó sì kọ́ pẹpẹ fún gbogbo àwọn ìrúbọ nínú ilé, ṣe iṣẹ́ àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì béèrè lọ́wọ́ àwọn òkú àti àwọn oṣó. Ó sì ṣe ọ̀pọ̀ búburú ní ojú Olúwa, ó sì mú un bínú.
6 Przeprowadził swojego syna przez ogień, uprawiał wróżbiarstwo i czary, ustanowił czarowników i czarnoksiężników. Bardzo wiele złego czynił w oczach PANA, pobudzając [go] do gniewu.
Ó fi àwọn ọmọ ara rẹ̀ rú ẹbọ nínú iná, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
7 Postawił też rzeźbę gaju, którą wykonał, w domu, o którym PAN powiedział do Dawida i do jego syna Salomona: W tym domu i w Jerozolimie, które wybrałem spośród wszystkich pokoleń Izraela, umieszczę swoje imię na wieki;
Ó sì gbé ère fínfín òrìṣà Aṣerah tí ó ti ṣe, ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí èmi ti yàn jáde lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò kọ orúkọ mi títí láéláé.
8 A już więcej nie dopuszczę, by noga Izraela opuściła ziemię, którą dałem ich ojcom, oby tylko pilnie przestrzegali wszystkiego, co im nakazałem, i całego prawa, które im nadał mój sługa Mojżesz.
Èmi kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli yẹ̀ kúrò láti ilẹ̀ tí èmi fi fún àwọn baba ńlá wọn tí ó bá jẹ́ wí pé wọn yóò ṣe àkíyèsí láti ṣe gbogbo ohun tí èmi ti paláṣẹ fún wọn kí wọn sì pa gbogbo òfin tí ìránṣẹ́ mi Mose fi fún wọn mọ́.”
9 Lecz oni nie słuchali. A Manasses zwiódł ich, aby czynili gorzej niż narody, które PAN wytracił przed synami Izraela.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tẹ́tí. Manase tàn wọ́n síwájú, bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n lè ṣe búburú ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa tí parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli lọ.
10 Wtedy PAN przemówił przez swoje sługi, proroków, mówiąc:
Olúwa sì wí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì pé,
11 Ponieważ Manasses, król Judy, dopuścił się tych obrzydliwości, czyniąc gorsze rzeczy niż wszystko, co czynili Amoryci, którzy byli przed nim, a przywiódł Judę do grzechu przez swoje bożki;
“Manase ọba Juda ti ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ohun ìríra. Ó ti ṣe ohun búburú jùlọ ju àwọn ará Amori lọ ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ tí ó sì ti ṣáájú Juda sínú ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn ère rẹ̀.
12 Dlatego tak mówi PAN, Bóg Izraela: Oto sprowadzę nieszczęście na Jerozolimę i na Judę, tak że każdemu, kto o tym usłyszy, zadzwoni w obu uszach.
Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, Èmi le è lọ mú irú ibi báyìí wá sórí Jerusalẹmu àti Juda kí gbogbo etí olúkúlùkù tí ó gbọ́ nípa rẹ̀ le è hó.
13 Rozciągnę bowiem nad Jerozolimą sznur Samarii i pion domu Achaba. I wytrę Jerozolimę, tak jak wyciera się miskę, a po wytarciu odwraca się dnem do góry.
Èmi yóò sì nà okùn ìwọ̀n kan tí a lò lórí Jerusalẹmu àti lórí Samaria àti òjé ìdiwọ̀n ti a lò lórí ilé Ahabu. Èmi yóò sì nu Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọkàn tí ń nu àwokòtò nù tí o ń nù un tí o sì ń dorí rẹ̀ kodò.
14 I porzucę resztę swojego dziedzictwa, i wydam je w ręce jego wrogów; staną się łupem i pastwą wszystkich swoich wrogów.
Èmi yóò sì kọ ìyókù àwọn ìní mi sílẹ̀ èmi yóò sì kó wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́. Wọn yóò sì di ìkógun àti ìjẹ fún gbogbo àwọn ọ̀tá wọn,
15 Ponieważ dopuszczali się tego, co złe w moich oczach, i drażnili mnie od dnia, kiedy ich ojcowie wyszli z Egiptu, aż do dziś.
nítorí pé wọ́n ti ṣe búburú ní ojú mi, wọ́n sì ti mú mi bínú láti ọjọ́ tí baba ńlá wọn ti jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí.”
16 Ponadto nawet krwi niewinnej Manasses przelał bardzo dużo, tak że napełnił [nią] Jerozolimę od krańca do krańca, nie licząc swojego grzechu, przez który przywiódł do grzechu Judę, czyniąc to, co złe w oczach PANA.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Manase pẹ̀lú ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ púpọ̀ tí ó kún Jerusalẹmu láti ìkangun dé ìkangun ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti mú Juda ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni, kí wọ́n lè ṣe ohun búburú ní ojú Olúwa.
17 A pozostałe dzieje Manassesa i wszystko, co czynił, i jego grzech, którego się dopuścił, czy nie są zapisane w księdze kronik królów Judy?
Ní ti iṣẹ́ ìyókù ti ìjọba Manase, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ṣé wọ́n kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
18 I Manasses zasnął ze swymi ojcami, i został pogrzebany w ogrodzie swego domu, w ogrodzie Uzzy. I Amon, jego syn, królował w jego miejsce.
Manase sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ọgbà ààfin rẹ̀, ọgbà Ussa. Amoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
19 Amon miał dwadzieścia dwa lata, kiedy zaczął królować, i królował dwa lata w Jerozolimie. Jego matka miała na imię Meszullemet [i była] córką Charusa z Jotba.
Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Orúkọ màmá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Meṣulemeti ọmọbìnrin Harusi: ó wá láti Jotba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
20 Czynił on to, co złe w oczach PANA, tak jak czynił jego ojciec Manasses.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa àti gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe.
21 Szedł wszystkimi drogami, którymi szedł jego ojciec, i służył bożkom, którym służył jego ojciec, i oddawał im pokłon;
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà baba rẹ̀: Ó sì ń sin àwọn ère tí baba rẹ̀ ń sìn, ó sì ń tẹrí rẹ̀ ba fún wọn.
22 Opuścił PANA, Boga swoich ojców, a nie szedł drogą PANA.
Ó sì kọ Olúwa Ọlọ́run baba rẹ̀ sílẹ̀ kò sì rìn ní ọ̀nà ti Olúwa.
23 I słudzy Amona uknuli spisek przeciw niemu, i zabili króla w jego domu.
Àwọn ìránṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ lórí rẹ̀ wọ́n sì lu ọba pa ní àárín ilé rẹ̀.
24 Wtedy lud tej ziemi zabił wszystkich, którzy uknuli spisek przeciw królowi Amonowi. I lud tej ziemi ustanowił w jego miejsce królem Jozjasza, jego syna.
Nígbà náà àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí ó dìtẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì fi Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ààyè rẹ̀.
25 A pozostałe dzieje Amona, które czynił, czy nie są zapisane w księdze kronik królów Judy?
Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ti ìjọba Amoni àti ohun tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
26 I pogrzebano go w jego grobie, w ogrodzie Uzzy. A jego syn Jozjasz królował w jego miejsce.
Wọ́n sì sin ín sínú isà òkú nínú ọgbà Ussa. Josiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< II Królewska 21 >