< I Samuela 19 >

1 Wtedy Saul mówił do swego syna Jonatana i do wszystkich swoich sług, aby zabili Dawida.
Saulu sọ fún Jonatani ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n pa Dafidi. Ṣùgbọ́n Jonatani fẹ́ràn Dafidi púpọ̀
2 Lecz Jonatan, syn Saula, bardzo miłował Dawida. I Jonatan doniósł Dawidowi, mówiąc: Mój ojciec Saul chce cię zabić. Teraz więc strzeż się do rana i siedź w ukryciu.
Jonatani sì kìlọ̀ fún Dafidi pé, “Baba mi Saulu wá ọ̀nà láti pa ọ́, kíyèsi ara rẹ di òwúrọ̀ ọ̀la; lọ sí ibi ìkọ̀kọ̀, kí o sì sá pamọ́ sí ibẹ̀.
3 A ja wyjdę i stanę przy swoim ojcu na polu, tam gdzie ty będziesz. Będę rozmawiał o tobie ze swoim ojcem, a cokolwiek zobaczę, powiadomię cię o tym.
Èmi yóò jáde lọ láti dúró ní ọ̀dọ̀ baba mi ní orí pápá níbi tí ó wà. Èmi yóò sọ̀rọ̀ fún un nípa à rẹ, èmi yóò sì sọ ohun tí òun bá wí fún ọ.”
4 Jonatan mówił więc dobrze o Dawidzie ze swym ojcem Saulem i powiedział mu: Niech król nie grzeszy przeciwko swemu słudze Dawidowi, gdyż on nie zgrzeszył przeciw tobie, a jego czyny [są] raczej dla ciebie bardzo pożyteczne:
Jonatani sọ̀rọ̀ rere nípa Dafidi fún Saulu baba rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Má ṣe jẹ́ kí ọba kí ó ṣe ohun tí kò dára fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀; nítorí tí kò ṣẹ̀ ọ́, ohun tí ó sì ṣe pé ọ púpọ̀.
5 On przecież narażał swoje życie i zabił Filistyna, i PAN dokonał wielkiego wybawienia dla całego Izraela. Sam [to] widziałeś i uradowałeś się. Dlaczego więc miałbyś grzeszyć przeciw niewinnej krwi i bez powodu zabić Dawida?
Ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu nígbà tí ó pa Filistini. Olúwa ṣẹ́ ogun ńlá fún gbogbo Israẹli, ìwọ rí i inú rẹ dùn. Ǹjẹ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Dafidi aláìṣẹ̀, tí ìwọ yóò fi pa á láìnídìí?”
6 I Saul posłuchał słów Jonatana, i przysiągł: Jak żyje PAN, nie zostanie zabity.
Saulu fetísí Jonatani, ó sì búra báyìí, “Níwọ́n ìgbà tí Olúwa bá ti ń bẹ láààyè, a kì yóò pa Dafidi.”
7 Jonatan zawołał więc Dawida i powtórzył mu wszystkie te słowa. Potem Jonatan przyprowadził Dawida do Saula i przebywał z nim, tak jak poprzednio.
Nítorí náà Jonatani pe Dafidi, ó sì sọ gbogbo àjọsọ wọn fún un. Ó sì mú un wá fún Saulu, Dafidi sì wà lọ́dọ̀ Saulu gẹ́gẹ́ bí i ti tẹ́lẹ̀.
8 Gdy znowu wybuchła wojna, Dawid wyruszył przeciw Filistynom i walczył z [nimi], i zadał im wielką klęskę tak, że uciekli przed nim.
Lẹ́ẹ̀kan an sí i ogun tún wá, Dafidi sì jáde lọ, ó sì bá àwọn ara Filistini jà. Ó sì pa wọn pẹ̀lú agbára, wọ́n sì sálọ níwájú u rẹ̀.
9 A zły duch od PANA opanował Saula, kiedy siedział w swym domu, trzymając włócznię w ręku, Dawid zaś grał [swą] ręką [melodię].
Ṣùgbọ́n ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí orí Saulu bí ó ti jókòó ní ilé e rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Bí Dafidi sì ti fọn ohun èlò orin olókùn,
10 I Saul chciał przybić Dawida włócznią do ściany, lecz ten wymknął się Saulowi i włócznia utkwiła w ścianie, a Dawid wybiegł i uciekł tej nocy.
Saulu sì wá ọ̀nà láti gún un mọ́ ògiri pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Saulu ti ju ọ̀kọ̀ náà mọ́ ara ògiri. Ní alẹ́ ọjọ́ náà Dafidi sì fi ara pamọ́ dáradára.
11 Potem Saul wysłał posłańców do domu Dawida, aby go pilnowali i rano zabili. Lecz Mikal, jego żona, powiedziała o tym Dawidowi: Jeśli nie ujdziesz z życiem tej nocy, jutro zostaniesz zabity.
Saulu rán ènìyàn sí ilé Dafidi láti ṣọ́ ọ kí wọ́n sì pa á ní òwúrọ̀. Ṣùgbọ́n Mikali, ìyàwó Dafidi kìlọ̀ fún un pé, “Tí o kò bá sá fún ẹ̀mí rẹ ní alẹ́ yìí, ní ọ̀la ni a yóò pa ọ́.”
12 Mikal spuściła więc Dawida przez okno, a on odszedł, uciekł i ocalał.
Nígbà náà Mikali sì gbé Dafidi sọ̀kalẹ̀ ó sì fi aṣọ bò ó.
13 A Mikal wzięła bożka i położyła na łożu, a poduszkę z koziej [sierści] umieściła pod jego głową i przykryła szatą.
Mikali gbé ère ó sì tẹ́ e lórí ibùsùn, ó sì fi irun ewúrẹ́ sí ibi orí rẹ̀.
14 Gdy Saul wysłał posłańców, aby porwali Dawida, powiedziała: Jest chory.
Nígbà ti Saulu rán ènìyàn láti lọ fi agbára mú Dafidi, Mikali wí pé, “Ó rẹ̀ ẹ́.”
15 Saul znowu wysłał posłańców, aby zobaczyli Dawida, nakazując: Przynieście go do mnie na łożu, abym go zabił.
Nígbà náà ni Saulu rán ọkùnrin náà padà láti lọ wo Dafidi ó sì sọ fún wọn pé, “Mú wa fún mi láti orí ibùsùn rẹ̀ kí èmi kí ó le pa á.”
16 A gdy posłańcy przyszli, oto na łożu był bożek, a poduszka z koziej skóry była pod jego głową.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ère ni ó bá lórí ibùsùn àti irun ewúrẹ́ ní orí ère náà.
17 I Saul powiedział do Mikal: Dlaczego mnie tak oszukałaś i wypuściłaś mego wroga, aby uszedł? Mikal odpowiedziała Saulowi: On mi powiedział: Puść mnie, dlaczego miałbym cię zabić?
Saulu wí fún Mikali pé, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí báyìí tí o sì jẹ́ kí ọ̀tá mi sálọ tí ó sì bọ́?” Mikali sọ fún un pé, “Ó wí fún mi, ‘Jẹ́ kí èmi ó lọ. Èéṣe tí èmi yóò fi pa ọ́?’”
18 Dawid uciekł więc i ocalał, następnie przybył do Samuela, do Rama, i opowiedział mu wszystko, co Saul mu uczynił. Potem wraz z Samuelem poszli do Najot i tam zamieszkali.
Nígbà tí Dafidi ti sálọ tí ó sì ti bọ́, ó sì lọ sọ́dọ̀ Samuẹli ní Rama ó sì sọ gbogbo ohun tí Saulu ti ṣe fún un. Òun àti Samuẹli lọ sí Naioti láti dúró níbẹ̀.
19 I doniesiono Saulowi: Oto Dawid jest w Najot, w Rama.
Ọ̀rọ̀ sì tọ Saulu wá pé, “Dafidi wà ní Naioti ní Rama,”
20 Wtedy Saul wysłał posłańców, aby pojmali Dawida. Gdy zobaczyli gromadę prorokujących proroków oraz Samuela stojącego na ich czele, Duch Boży zstąpił na posłańców i oni także zaczęli prorokować.
Saulu sì rán àwọn ènìyàn láti fi agbára mú Dafidi wá ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Samuẹli dúró níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì wá sórí àwọn arákùnrin Saulu àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀.
21 Kiedy doniesiono o tym Saulowi, wysłał innych posłańców, lecz i oni prorokowali. Saul wysłał i trzecich posłańców, lecz także i ci prorokowali.
Wọ́n sì sọ fún Saulu nípa rẹ̀, ó sì rán ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn lọ àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀. Saulu tún rán oníṣẹ́ lọ ní ìgbà kẹta, àwọn náà bẹ̀rẹ̀ sí ní sọtẹ́lẹ̀.
22 Potem on sam poszedł do Rama i gdy przyszedł do wielkiej studni, która [jest] w Seku, zapytał: Gdzie jest Samuel i Dawid? Odpowiedziano mu: Oto [są] w Najot, w Rama.
Nígbẹ̀yìn, òun fúnra rẹ̀ sì lọ sí Rama ó sì dé ibi àmù ńlá kan ní Seku. Ó sì béèrè, “Níbo ni Samuẹli àti Dafidi wà?” Wọ́n wí pé, “Wọ́n wà ní ìrékọjá ní Naioti ní Rama.”
23 I szedł stamtąd do Najot w Rama, lecz na niego też zstąpił Duch Boży, tak że idąc, prorokował, aż przyszedł do Najot w Rama.
Saulu sì lọ sí Naioti ni Rama. Ṣùgbọ́n, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e lórí ó sì ń lọ lọ́nà, ó sì ń sọtẹ́lẹ̀ títí tí ó fi dé Naioti.
24 I zdjął z siebie szaty i także prorokował przed Samuelem, leżąc nagi przez cały dzień i całą noc. Stąd powiedzenie: Czyż i Saul między prorokami?
Ó sì bọ́ aṣọ rẹ̀, òun pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú Samuẹli. Ó sì dùbúlẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà àti ní òru. Ìdí nìyìí tí àwọn ènìyàn fi wí pé, “Ṣé Saulu náà wà lára àwọn wòlíì ni?”

< I Samuela 19 >