< Zachariasza 1 >

1 Miesiąca ósmego roku wtórego Daryjusza stało się słowo Pańskie do mnie Zacharyjasza, syna Barachyjaszowego, syna Iddowego, proroka, mówiąc:
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 Rozgniewał się Pan na ojców waszych bardzo.
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 Przetoż rzecz do nich: Tak mówi Pan zastępów: Nawróćcie się do mnie, mówi Pan zastępów, a nawrócę się do was, mówi Pan zastępów.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Nie bądźcież jako ojcowie wasi, na których wołali ojcowie pierwsi, mówiąc: Tak mówi Pan zastępów: Nawróćcież się teraz od złych dróg waszych, i od złych spraw waszych; ale nie usłuchali, ani dbali na mię, mówi Pan.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 Gdzież są ojcowie wasi, i prorocy? Izali na wieki żyć będą?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Wszakże izali słowa moje i ustawy moje, którem rozkazał prorokom, sługom moim, nie zasięgły ojców waszych? tak, że nawróciwszy się rzekli: Jako nam Pan zastępów uczynić umyślił według dróg naszych i według uczynków naszych, tak nam uczynił.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 Dnia dwudziestego i czwartego jedenastego miesiąca (ten jest miesiąc Sebat) roku wtórego Daryjuszowego stało się słowo Pańskie do Zacharyjasza, syna Barachyjaszowego, syna Iddowego, proroka, mówiąc:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 Widziałem w nocy, a oto mąż jechał na koniu rydzym, który stał między mirtami, które były w nizinie, a za nim konie rydze, czarne i białe.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 Tedym rzekł: Co zacz są ci, panie mój? I rzekł do mnie Anioł rozmawiający zemną: Ja tobie okażę, co zacz są.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 I odpowiedział mąż, który stał między mirtami, i rzekł: Ci są, których posłał Pan, aby przeszli ziemię.
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 I odpowiedzieli Aniołowi Pańskiemu stojącemu między mirtami, i rzekli: Przeszliśmy ziemię, a oto wszystka ziemia bezpieczeństwa i pokoju używa.
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 Tedy odpowiedział Anioł Pański, i rzekł: O Panie zastępów! i dokądże się nie zmiłujesz nad Jeruzalemem, i nad miastami Judzkiemi, na któreś się gniewał już siedmdziesiąt lat?
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 I odpowiedział Pan Aniołowi onemu, który mówił zemną, słowy dobremi, słowy pociesznemi.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 I rzekł do mnie Anioł, który mówił zemną: Wołaj a rzecz: Tak mówi Pan zastępów: Zapaliłem się za Jeruzalemem i za Syonem gorliwością wielką.
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 A gniewam się bardzo na te narody, które używają pokoju; bo gdym się Ja trochę zagniewał, tedy one pomagały do złego.
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 Przetoż tak mówi Pan: Nawróciłem się do Jeruzalemu w miłosierdziu, dom mój zbudowany będzie w niem, mówi Pan zastępów, i sznur rozciągniony będzie na Jeruzalem.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 Jeszcze wołaj, mówiąc: Tak mówi Pan zastępów: Jeszcze się osadzą miasta moje dla obfitości dobrego; bo jeszcze Pan Syon pocieszy, i obierze jeszcze Jeruzalem.
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 Tedym podniósł oczy swe i ujrzałem, a oto cztery rogi.
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 I rzekłem do Anioła, który mówił zemną: Cóż to jest? I rzekł do mnie: Teć są rogi, które rozrzuciły Judę i Izraela i Jeruzalem.
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 Ukazał mi też Pan czterech kowali.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 I rzekłem: Cóż ci idą czynić? I odpowiedział, mówiąc: Teć są rogi, które rozrzuciły Judę, tak, iż żaden nie mógł podnieść głowy swojej; przetoż ci przyszli, aby je przestraszyli, i strącili rogi tych narodów, które podniosły róg przeciwko ziemi Judzkiej, aby ją rozrzuciły.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

< Zachariasza 1 >