< Psalmów 99 >

1 Pan króluje, niechże zadrżą narody; siedzi między Cherubinami, niechże się poruszy ziemia.
Olúwa jẹ ọba; jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.
2 Pan na Syonie wielki, a wywyższony nad wszystkie narody.
Olúwa tóbi ní Sioni; Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.
3 Niech wysławiają imię twoje wielkie i straszne; albowiem święte jest.
Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.
4 Moc zaiste królewska miłuje sąd; albowiemeś ty ustanowił prawa; sąd i sprawiedliwość w Jakóbie ty wykonujesz.
Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo, ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀; ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.
5 Wywyższajcie Pana, Boga naszego, a kłaniajcie się u podnóżka nóg jego; bo święty jest.
Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.
6 Mojżesz i Aaron między kapłanami jego, a Samuel między wzywającymi imienia jego, wołali do Pana, a on ich wysłuchał.
Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀ Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀ wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.
7 W słupie obłokowym mówił do nich; a gdy strzegli świadectw jego i ustaw, które im podał,
Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀, wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.
8 Panie, Boże nasz! tyś ich wysłuchiwał; Boże! bywałeś im miłościwym, i gdyś ich karał dla występków ich.
Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn; ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.
9 Wywyższajcie Pana, Boga naszego, a kłaniajcie się na górze świętej jego; albowiem święty jest Pan, Bóg nasz.
Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀ nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.

< Psalmów 99 >