< Psalmów 92 >

1 Psalm a pieśń na dzień sobotni. Dobra rzecz jest wysławiać Pana, a śpiewać imieniowi twemu, o Najwyższy.
Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 Opowiadać z poranku miłosierdzie twoje, i prawdę twoję na każdą noc,
láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
3 Na instrumencie o dziesięciu strunach, na lutni, i na harfie z śpiewaniem.
lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 Albowiemeś mię rozweselił, Panie! sprawami twemi; o sprawach rąk twoich śpiewać będę.
Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 O jako wielmożne są sprawy twoje, Panie! bardzo głębokie są myśli twoje.
Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 Człowiek bydlęcy nie zna, a głupi nie zrozumiewa tego,
Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 Iż wyrastają niezbożnicy jako ziele, a kwitną wszyscy, którzy czynią nieprawość, aby byli wykorzenieni aż na wieki;
nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
8 Ale ty, o Najwyższy! jesteś Panem na wieki.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 Albowiem, oto nieprzyjaciele twoi, Panie! albowiem oto nieprzyjaciele twoi zginą; rozproszeni będą wszyscy, którzy czynią nieprawość.
Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
10 Ale róg mój wywyższysz jako jednorożców; pokropiony będę olejkiem świeżym.
Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 I ujrzy oko moje nieszczęście tych, co na mię czyhają; o złośnikach, którzy powstawają przeciwko mnie, usłyszą uszy moje.
Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
12 Sprawiedliwy jako palma zakwitnie, jako cedra na Libanie rozmnoży się.
Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
13 Wszczepieni w domu Pańskim, w sieniach Boga naszego zakwitną.
tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 Nawet i w sędziwości przyniosą owoc, czerstwymi i zielonymi będą;
Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 Aby to opowiadano, że uprzejmym jest Pan, skała moja, a że w nim nie masz żadnej nieprawości.
láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”

< Psalmów 92 >