< Psalmów 90 >

1 Modlitwa Mojżesza, męża Bożego. Panie! tyś bywał ucieczką naszą od narodu do narodu.
Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
2 Pierwej niżli góry stanęły i niżliś wykształtował ziemię, i okrąg świata, oto zaraz od wieku aż na wieki tyś jest Bogiem.
Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
3 Ty znowu człowieka w proch obracasz, a mówisz: Nawróćcie się synowie ludzcy.
Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
4 Albowiem tysiąc lat przed oczyma twemi są jako dzień wczorajszy, który przeminął, i jako straż nocna.
Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
5 Powodzią porywasz ich; są jako sen, i jako trawa, która z poranku rośnie.
Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
6 Z poranku kwitnie i rośnie; ale w wieczór bywa pokoszona, i usycha.
Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
7 Albowiem od gniewu twego giniemy, a popędliwością twoją jesteśmy przestraszeni.
A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
8 Położyłeś nieprawości nasze przed sobą, tajne występki nasze przed jasnością oblicza twego.
Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
9 Skąd wszystkie dni nasze nagle przemijają dla gniewu twego; jako słowa niszczeją lata nasze.
Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
10 Dni wieku naszego jest lat siedmdziesiąt, a jeźli kto duższy, lat ośmdziesiąt, a to, co najlepszego w nich, tylko kłopot i nędza, a gdy to pominie, tedy prędko odlatujemy.
Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
11 Ale któż zna srogość gniewu twego? albo kto bojąc się ciebie zna zapalczywość twoję?
Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
12 Nauczże nas obliczać dni naszych, abyśmy przywiedli serce do mądrości.
Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
13 Nawróćże się, Panie! dokądże odwłaczasz? zlitujże się nad sługami twymi.
Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
14 Nasyćże nas z poranku miłosierdziem twojem; tak, abyśmy wesoło śpiewać i radować się mogli po wszystkie dni nasze.
Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
15 Rozweselże nas według dni, którycheś nas utrapił, według lat, którycheśmy doznali złego.
Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
16 Niech będzie znaczna przy sługach twoich sprawa twoja, a chwała twoja przy synach ich.
Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
17 Niech będzie przyjemność Pana, Boga naszego, przy nas, a sprawę rąk naszych utwierdź między nami, sprawę rąk naszych utwierdź, Panie!
Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.

< Psalmów 90 >