< Psalmów 74 >

1 Pieśń wyuczająca, podana Asafowi. Przeczżeś nas, o Boże! do końca odrzucił? Przeczże się rozpaliła zapalczywość twoja przeciwko owcom pastwiska twego?
Maskili ti Asafu. Ọlọ́run, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ wá sílẹ̀ títí láé? Èéṣe tí ìbínú rẹ̀ fi dìde sí àwọn àgùntàn pápá rẹ?
2 Wspomnij na zgromadzenie twoje, któreś sobie zdawna nabył i odkupił, na pręt dziedzictwa twego, na tę górę Syon, na której mieszkasz.
Rántí àwọn ènìyàn tí ìwọ ti rà nígbà àtijọ́, ẹ̀yà ilẹ̀ ìní rẹ, tí ìwọ ti rà padà. Òkè Sioni, níbi tí ìwọ ń gbé.
3 Pospieszże się na srogie popustoszenie; a jako wszystko poburzył nieprzyjaciel w świątnicy!
Yí ẹsẹ̀ rẹ padà sí ìparun ayérayé wọn, gbogbo ìparun yìí tí ọ̀tá ti mú wá sí ibi mímọ́.
4 Ryczeli nieprzyjaciele twoi w pośrodku zgromadzenia twego, a na znak tego zostawili wiele chorągwi swoich.
Àwọn ọ̀tá rẹ ń bú ramúramù láàrín ènìyàn rẹ, wọ́n ń gbé àsíá wọn sókè fún àmì.
5 Za rycerza miano tego, który się z wysoka z siekierą zanosił, rąbiąc drzewo wiązania jego.
Wọ́n ń rí bí ọkùnrin tí ó gbé àáké rẹ̀ sókè láti gé igi igbó dídí.
6 A teraz już i rzezania jego na porząd siekierami i młotami tłuką.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, iṣẹ́ ọnà fínfín, ni wọ́n fi àáké wó lulẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan náà.
7 Założyli ogień w świątnicy twojej, a obaliwszy na ziemię, splugawili przybytek imienia twego.
Wọ́n sun ibi mímọ́ rẹ lulẹ̀ wọ́n ba ibùgbé orúkọ rẹ jẹ́.
8 Mówili w sercu swojem: Zburzmy je pospołu; popalili wszystkie przybytki Boże w ziemi.
Wọ́n wí ní ọkàn wọn. “Àwa ó run wọ́n pátápátá!” Wọ́n sun gbogbo ibi ìjọ́sìn Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà.
9 Znaków naszych nie widzimy: już niemasz proroka, i niemasz między nami, któryby wiedział, póki to ma trwać.
A kò fún wa ní àmì iṣẹ́ ìyanu kankan; kò sí wòlíì kankan ẹnìkankan wa kò mọ ìgbà tí eléyìí yóò dà.
10 Dokądże, o Boże! przeciwnik będzie urągać? izali nieprzyjaciel będzie bluźnił imię twoje aż na wieki?
Àwọn ọ̀tá yóò ti kùn sí ọ pẹ́ tó, Ọlọ́run? Àwọn ọ̀tá yóò ha ba orúkọ rẹ jẹ́ títí láé?
11 Przeczże zstrzymujesz rękę twoję; a prawicy swej z zanadrza swego cale nie dobędziesz?
Èéṣe tí ìwọ fi dá ọwọ́ rẹ dúró, ọwọ́ ọ̀tún rẹ? Mú un kúrò nínú ìṣẹ́po aṣọ rẹ kí o sì run wọ́n!
12 Wszakeś ty, Boże! zdawna królem moim; ty sprawujesz hojne zbawienie w pośród ziemi.
Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run ni ọba mi láti ìgbà pípẹ́; Ó mú ìgbàlà wá sórí ilẹ̀ ayé.
13 Tyś mocą twoją rozdzielił morze, a potarłeś głowy wielorybów w wodach.
Ìwọ ni ó la òkun sílẹ̀ nípa agbára rẹ; ìwọ fọ́ orí ẹ̀mí búburú nínú omi.
14 Tyś skruszył głowę Lewiatana, dałeś go za pokarm ludowi na puszczy.
Ìwọ fọ́ orí Lefitani túútúú, o sì fi ṣe oúnjẹ fun àwọn ẹ̀dá tí ń gbé inú ijù tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ sì ni alẹ́ pẹ̀lú; ìwọ fi ìdí oòrùn àti òṣùpá lélẹ̀.
15 Tyś przerwał źródła i potoki; tyś osuszył rzeki bystre.
Ìwọ ya orísun omi àti ìṣàn omi; Ìwọ mú kí odò tó ń sàn gbẹ.
16 Twójci jest dzień, twoja też i noc; tyś uczynił światło i słońce.
Tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ ni òru pẹ̀lú; ìwọ yà oòrùn àti òṣùpá.
17 Tyś założył wszystkie granice ziemi; lato i zimę tyś sprawił.
Ìwọ pààlà etí ayé; Ìwọ dá ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òtútù.
18 Wspomnijże na to, że nieprzyjaciel zelżył Pana, a lud szalony jako urąga imieniowi twemu.
Rántí bí àwọn ọ̀tá ń kẹ́gàn rẹ, Olúwa bí àwọn aṣiwèrè ènìyàn ti ń ba orúkọ rẹ jẹ́.
19 Nie podawajże tej kupie duszy synogarlicy twojej; na stadko ubogich twoich nie zapominaj na wieki.
Má ṣe fi ẹ̀mí àdàbà rẹ fún ẹranko igbó búburú; má ṣe gbàgbé ẹ̀mí àwọn ènìyàn rẹ tí a ń pọ́n lójú títí láé.
20 Obejrzyj się na przymierze twoje; albowiem i najciemniejsze kąty ziemi pełne jaskiń drapiestwa.
Bojú wo májẹ̀mú rẹ, nítorí ibi òkùnkùn ayé kún fún ibùgbé ìkà.
21 Niechajże nędznik nie odchodzi z hańbą; ubogi i żebrak niechaj chwali imię twoje.
Má ṣe jẹ́ kí àwọn aninilára padà sẹ́yìn nínú ìtìjú jẹ́ kí àwọn aláìní àti tálákà yin orúkọ rẹ.
22 Powstańże, o Boże! ujmij się o sprawę twoję; wspomnij na pohańbienie twoje, które się dzieje od szalonych na każdy dzień.
Dìde, Ọlọ́run, gba ẹjọ́ ara rẹ rò; rántí bí àwọn aṣiwèrè ti ń kẹ́gàn rẹ ní gbogbo ọjọ́.
23 Nie zapominajże wykrzykania nieprzyjaciół twoich, i huku tych, co przeciwko tobie powstawają, który się ustawicznie sili.
Má ṣe gbàgbé ohùn àwọn ọ̀tá rẹ, bíbú àwọn ọ̀tá rẹ, tí ó ń pọ̀ sí i nígbà gbogbo.

< Psalmów 74 >