< Psalmów 58 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi, jako: Nie zatracaj, pieśń złota Dawidowa. O zgromadzenie! Izali poprawdzie sprawiedliwość mówicie? A uprzejmież sądzicie, wy synowie ludzcy?
Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́ ẹ̀yin ìjọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́ ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?
2 Owszem, radniej w sercu nieprawości knujecie, a gwałty rąk waszych na ziemi odważacie.
Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo, ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.
3 Odłączyli się niezbożnicy zaraz od narodzenia; pobłądzili zaraz z żywota matki swej, mówiąc kłamstwo.
Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà, lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.
4 Jad mają w sobie, jako wężowy, jako jad żmii głuchej, która zatula ucho swoje,
Oró wọn dàbí oró ejò, wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,
5 Aby nie słyszała głosu zaklinacza, ani czarownika w czarach biegłego.
tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú, bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.
6 O Boże! pokruszże zęby ich w ustach ich; połam, Panie! lwiąt trzonowe zęby.
Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run; ní ẹnu wọn, ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.
7 Niech się rozpłyną jako woda, niech się wniwecz obrócą; niech będą jako ten, który naciąga łuk, wszakże się strzały jego łamią.
Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ; nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.
8 Jako ślimak, który schodzi i niszczeje; jako martwy płód niewieści niech nie oglądają słońca.
Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.
9 Ciernie wasze pierwej niż wypuszczą tarny swoje, za zielona w gniewie Bożym jako wichrem porwane będą.
Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún; bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.
10 I będzie się weselił sprawiedliwy, gdy ujrzy pomstę; nogi swoje umyje we krwi niepobożnego.
Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn, nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.
11 I rzecze każdy: Zaprawdęć sprawiedliwy odniesie pożytek z sprawiedliwości swojej; zaisteć jest Bóg, który sądzi na ziemi.
Àwọn ènìyàn yóò wí pé, “Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo; lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”

< Psalmów 58 >