< Psalmów 51 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. Gdy do niego przyszedł Natan prorok, potem jak był wszedł do Betsaby. Zmiłuj się nademną, Boże! według miłosierdzia twego; według wielkich litości twoich zgładź nieprawości moje.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀ kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.
2 Omyj mię doskonale od nieprawości mojej, a od grzechu mego oczyść mię.
Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!
3 Albowiem ja znam nieprawość moję, a grzech mój przedemną jest zawżdy.
Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi, nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.
4 Tobie, tobiem samemu zgrzeszył, i złem przed oczyma twemi uczynił, abyś był sprawiedliwy w mowie twojej, i czystym w sądzie twoim.
Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀, kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀, kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.
5 Oto w nieprawości poczęty jestem, a w grzechu poczęła mię matka moja.
Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.
6 Oto się kochasz w prawdzie wewnętrznej, a skrytą mądrość objawiłeś mi.
Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú; ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.
7 Oczyść mię, isopem, a oczyszczon będę; omyj mię, a nad śnieg wybielony będę.
Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́; fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.
8 Daj mi słyszeć radość i wesele, a niech się rozradują kości moje, któreś pokruszył.
Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn; jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.
9 Odwróć oblicze twoje od grzechów moich, a zgładź wszystkie nieprawości moje.
Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.
10 Serce czyste stwórz we mnie, o Boże! a ducha prawego odnów we wnętrznościach moich.
Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run, kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.
11 Nie odrzucaj mię od oblicza twego, a Ducha swego świętego nie odbieraj odemnie.
Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ, kí o má ṣe gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.
12 Przywróć mi radość zbawienia twego, a duchem dobrowolnym podeprzyj mię.
Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá, kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.
13 Tedy będę nauczał przestępców dróg twoich, aby się grzesznicy do ciebie nawrócili.
Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ, àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.
14 Wyrwij mię z pomsty za krew, o Boże, Boże zbawienia mojego! a język mój będzie wysławiał sprawiedliwość twoję.
Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi, ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.
15 Panie! otwórz wargi moje, a usta moje opowiadać będą chwałę twoję.
Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo, àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.
16 Albowiem nie pragniesz ofiar, choćbym ci je dał, ani całopalenia przyjmiesz.
Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá; Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.
17 Ofiary Bogu przyjemne duch skruszony; sercem skruszonem i strapionem nie pogardzisz, o Boże!
Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.
18 Dobrze uczyń według upodobania twego Syonowi; pobubuj mury Jeruzalemskie.
Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni, ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.
19 Tedy przyjmiesz ofiary sprawiedliwości, ofiary ogniste, i całopalenia; tedy cielce ofiarować będą na ołtarzu twoim.
Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo, pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun, nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.

< Psalmów 51 >