< Psalmów 45 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi z synów Korego na Sosannim psalm nauczający, a pieśń weselna. Wydało serce moje słowo dobre; rozprawiać będę pieśni moje, o królu! język mój będzie jako pióro prędkiego pisarza.
Fún adarí orin. Tí ohun orin “Lílì.” Ti orin àwọn ọmọ Kora. Maskili. Orin ìgbéyàwó. Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.
2 Piękniejszyś nad synów ludzkich; rozlała się wdzięczność po wargach twoich, przeto, że cię pobłogosławił Bóg aż na wieki.
Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ: a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè: nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.
3 Przypasz miecz twój na biodra, o mocarzu! pokaż chwałę twoję, i zacności twoje.
Gba idà rẹ mọ́ ìhà rẹ, ìwọ alágbára jùlọ wọ ara rẹ ní ògo àti ọláńlá.
4 A w dostojności twojej szczęśliwie wywiedź z słowem prawdy, cichości, i sprawiedliwości, a dokaże strasznych rzeczy prawica twoja.
Nínú ọláńlá rẹ, máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́, ìwà tútù àti òtítọ́; jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ohun ẹ̀rù.
5 Strzały twoje ostre; od nich narody pod cię upadną, a serce nieprzyjaciół królewskich przenikną.
Jẹ́ kí ọfà mímú rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
6 Stolica twoja, o Boże! na wieki wieków; laska sprawiedliwości jest laska królestwa twego.
Ọlọ́run láé, àti láéláé ni ìtẹ́ rẹ, ọ̀pá aládé ìjọba rẹ, ọ̀pá aládé òtítọ́ ni.
7 Umiłowałeś sprawiedliwość, a nienawidziłeś nieprawości; przetoż pomazał cię, o Boże! Bóg twój olejkiem wesela nad uczęstników twoich.
Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run rẹ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ, nípa fífi àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́.
8 Myrrą, aloe, i kassyją wszystkie szaty twoje pachną, gdy wychodzisz z pałaców z kości słoniowych urobionych, nad tych, którzy cię uweselają.
Gbogbo aṣọ rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjìá àti aloe àti kasia; láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú rẹ̀ dùn.
9 Córki królewskie są między twemi zacnemi białemi głowami; stanęła małżonka po prawicy twojej w kosztownem złocie z Ofir.
Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba wà nínú àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró nínú wúrà Ofiri.
10 Słuchajże córko, a obacz, i nakłoń ucha twego, a zapomnij narodu twego, i domu ojca twojego.
Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí rẹ sí mi gbàgbé àwọn ènìyàn rẹ àti ilé baba rẹ.
11 A zakocha się król w piękności twojej, albowiem on jest Panem twoim; przetoż kłaniaj się przed nim.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà rẹ gidigidi nítorí òun ni olúwa rẹ kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.
12 Tyryjczycy także z upominkami przed obliczem twojem kłaniać się będą, najbogatsi z narodów.
Ọmọbìnrin ọba Tire yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojúrere rẹ̀.
13 Wszystka zacność córki królewskiej jest wewnątrz, a szaty jej bramowane są złotem.
Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárín ilé rẹ̀, iṣẹ́ wúrà ọnà abẹ́rẹ́ ní aṣọ rẹ̀.
14 W odzieniu haftowanem przywiodą ją do króla; także panny za nią, towarzyszki jej, przywiodą do ciebie.
Nínú aṣọ olówó iyebíye ni a mú un tọ́ ọba wá, àwọn wúńdíá ẹgbẹ́ rẹ̀ tẹ̀lé e, wọ́n sí mú un tọ̀ ọ́ wá.
15 Przywiodą je z weselem i z radością, a wnijdą na pałac królewski.
Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn wọ́n sì wọ ààfin ọba.
16 Miasto ojców twych będziesz mieć synów twych, których postanowisz książętami po wszystkiej ziemi.
Ọmọ rẹ̀ ni yóò gba ipò baba rẹ̀ ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.
17 Wspominać będę imię twoje od każdego rodzaju do rodzaju: dlatego cię narody wysławiać będą na wieki wieków.
Èmí yóò máa rántí orúkọ rẹ̀ ní ìran gbogbo, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.

< Psalmów 45 >