< Psalmów 44 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi z synów Korego psalm nauczający. Boże! uszami naszemi słyszeliśmy; ojcowie nasi powiadali nam o sprawach, któreś czynił za dni ich, za dni starodawnych.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili. À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run; àwọn baba wa tí sọ fún wa ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn, ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.
2 Tyś ręką swą wypędził pogan, a onycheś wszczepił; wytraciłeś narody, a onycheś rozkrzewił.
Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde, Ìwọ sì gbin àwọn baba wa; ìwọ run àwọn ènìyàn náà Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.
3 Bo nie przez miecz swój posiedli ziemię, i ramię ich nie wybawiło ich, ale prawica twoja i ramię twoje, a światłość oblicza twego, przeto, żeś ich upodobał sobie.
Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ; àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.
4 Tyś sam król mój, o Boże! sprawże wielkie wybawienie Jakóbowi.
Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi, ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.
5 Przez cię nieprzyjaciół naszych porażaliśmy; w imieniu twojem deptaliśmy powstawających przeciwko nam.
Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú; nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀,
6 Bom w łuku moim nie ufał, ani miecz mój obronił mię;
èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi, idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,
7 Aleś nas ty wybawiał od nieprzyjaciół naszych, a nienawidzących nas zawstydzałeś.
ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa, ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.
8 Przetoż chlubimy się w tobie, Boże! na każdy dzień, a imię twoje na wieki wysławiamy. (Sela)
Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́, àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. (Sela)
9 Ale teraz odrzuciłeś i zawstydziłeś nas, a nie wychodzisz z wojskami naszemi.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá, Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.
10 Sprawiłeś, żeśmy tył podali nieprzyjacielowi, a ci, którzy nas mają w nienawiści, rozchwycili między się dobra nasze.
Ìwọ ti bá wa jà, ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa, àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa, wọ́n sì fi ipá gba oko wa.
11 Podałeś nas jako owce na żer, a między pogan rozproszyłeś nas.
Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn, Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.
12 Sprzedałeś lud twój za nic, a nie podniosłeś ceny ich.
Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré, Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.
13 Podałeś nas na wzgardę sąsiadom naszym, na szyderstwo i na pośmiech tym, którzy są około nas.
Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa, ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.
14 Wystawiłeś nas na przypowieść między poganami, tak, że nad nami narody głową kiwają.
Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.
15 Na każdy dzień wstyd mój jest przedemną, a hańba twarzy mojej okrywa mię.
Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́, ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,
16 Dla głosu tego, który mię sromoci i potwarza, dla nieprzyjaciela, i tego, który się mści.
nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.
17 To wszystko przyszło na nas; a wżdyśmy cię nie zapomnieli, aniśmy wzruszyli przymierza twego.
Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa, síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.
18 Nie cofnęło się nazad serce nasze, ani się uchyliły kroki nasze od ścieżki twojej,
Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
19 Chociażeś nas był potarł, wrzuciwszy nas na miejsce smoków, i okryłeś nas cieniem śmierci.
Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá, ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú, tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.
20 Byśmyć byli zapomnieli imienia Boga naszego, a podnieśli ręce nasze do Boga cudzego,
Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.
21 Iazliby się był Bóg o tem nie pytał? gdyż on wie skrytości serca.
Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?
22 Aleć nas dla ciebie zabijają na każdy dzień; poczytają nas jako owce na rzeź zgotowane.
Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́ a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.
23 Ocuć się; przeczże śpisz, Panie! Przebudź się, nie odrzucaj nas na wieki.
Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn? Dìde fúnra rẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.
24 Przeczże oblicze twoje ukrywasz, a zapominasz utrapienia naszego i ucisku naszego?
Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́ tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?
25 Albowiem potłoczona jest aż do prochu dusza nasza, a przylgnął do ziemi żywot nasz.
Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku; ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.
26 Powstańże na ratunek nasz, a odkup nas dla miłosierdzia twego.
Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́; rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.

< Psalmów 44 >