< Psalmów 42 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi z synów Korego pieśń ćwicząca. Jako jeleń krzyczy do strumieni wód, tak dusza moja woła do ciebie, o Boże!
Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora. Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
2 Pragnie dusza moja do Boga, do Boga żywego, mówiąc: Kiedyż przyjdę, a okażę się przed obliczem Bożem?
Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè. Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
3 Łzy moje są mi miasto chleba we dnie i w nocy, gdy mi mówią co dzień: Kędyż jest Bóg twój?
Oúnjẹ mi ni omijé mi ní ọ̀sán àti ní òru, nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé, “Ọlọ́run rẹ dà?”
4 Na to wspominając wylewam sam sobie duszę moję, żem bywał w poczcie innych, i chadzałem z nimi do domu Bożego, z wesołym głosem, i z chwałą, w mnóstwie weselących się.
Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí, èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi: èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ, èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
5 Przeczże się smucisz, duszo moja! a przecz sobą trwożysz we mnie? Czekaj na Boga; albowiem go jeszcze będę wysławiał za wielkie wybawienie twarzy jego.
Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín, Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
6 Boże mój! dusza moja tęskni sobie we mnie; przetoż na cię wspominam w ziemi Jordańskiej i Hermońskiej, na górze Mizar.
Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi: nítorí náà, èmi ó rántí rẹ láti ilẹ̀ Jordani wá, láti Hermoni láti òkè Mibsari.
7 Przepaść przepaści przyzywa, na szum upustów twoich: wszystkie powodzi twoje i nawałności twoje na mię się zwaliły.
Ibú omi ń pe ibú omi nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀ gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀ bò mí mọ́lẹ̀.
8 Wszakże we dnie udzieli mi Pan miłosierdzia swego, a w nocy piosnka jego będzie ze mną, i modlitwa do Boga żywota mego.
Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀, àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
9 Rzekę Bogu, skale mojej: Przeczżeś mię zapomniał? I czemu smutno chodzę dla uciśnienia od nieprzyjaciela?
Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi, “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi? Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́, nítorí ìnilára ọ̀tá?”
10 Jest jako rana w kościach moich, gdy mi urągają nieprzyjaciele moi, mówiąc do mnie na każdy dzień: Kędy jest Bóg twój?
Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí, bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́. “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
11 Przeczże się smucisz, duszo moja? a przecz sobą trwożysz we mnie? Czekaj na Boga; albowiem go jeszcze będę wysławiał, gdyż on jest wielkiem zbawieniem twarzy mojej, i Bogiem moim.
Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.

< Psalmów 42 >