< Psalmów 40 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. Z żądością oczekiwałem Pana; a skłonił się ku mnie, i wysłuchał wołanie moje;
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa; ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
2 I wyciągnął miecz z dołu szumiącego i z błota lgnącego, a postawił na skale nogi moje, i utwierdził kroki moje;
Ó fà mí yọ gòkè láti inú ihò ìparun, láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta, ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
3 A włożył w usta moje pieśń nową, chwałę należącą Bogu naszemu, co gdy wiele ich ogląda, ulękną się, a będą mieć nadzieję w Panu.
Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu, àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa. Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
4 Błogosławiony człowiek, który pokłada w Panu nadzieję swoję, a nie ogląda się na hardych, ani na tych, którzy się unoszą za kłamstwem.
Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga, tàbí àwọn tí ó yapa lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
5 Wieleś uczynił, Panie, Boże mój! cudów twoich, a myśli twoich o nas nikt porządnie wyliczyć nie może przed tobą; chciałlibym je wypowiedzieć i wymówić, daleko ich więcej, niżby wypowiedziane być mogły.
Olúwa Ọlọ́run mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe. Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa; ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ, tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn, wọ́n ju ohun tí ènìyàn le è kà lọ.
6 Ofiary i obiaty nie chciałeś, aleś mi przekłół uszy; całopalenia i ofiary za grzech nie żądałeś.
Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́, ìwọ ti ṣí mi ní etí. Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò béèrè.
7 Tedym rzekł: Oto idę; w księgach napisano o mnie;
Nígbà náà ni mo wí pé, “Èmi nìyí; nínú ìwé kíká ni a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
8 Abym czynił wolę twoję, Boże mój! pragnę, albowiem zakon twój jest w pośrodku wnętrzności moich.
Mo ní inú dídùn láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ, ìwọ Ọlọ́run mi, òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
9 Opowiadałem sprawiedliwość twoję w zgromadzeniu wielkiem; oto warg moich nie zawściągnąłem, ty wiesz, Panie!
Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà láàrín àwùjọ ńlá; wò ó, èmi kò pa ètè mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀, ìwọ Olúwa.
10 Sprawiedliwości twojej nie ukryłem w pośród serca mego, prawdę twoję i zbawienie twoje opowiadałem; nie taiłem miłosierdzia twego i prawdy twojej w zgromadzeniu wielkiem.
Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi; èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ. Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
11 Przetoż ty, Panie! nie zawściągaj odemnie litości twoich; miłosierdzie twoje i prawda twoja niech mię zawżdy strzegą.
Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
12 Albowiem ogarnęły mię nieszczęścia, którym niemasz liczby; doścignęły mię nieprawości moje, tak, że przejrzeć nie mogę; rozmnożyły się nad włosy głowy mojej, a serce moje opuściło mię.
Nítorí pé àìníye ibi ni ó yí mi káàkiri, ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi, títí tí èmi kò fi ríran mọ́; wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, àti wí pé àyà mí ti kùnà.
13 Raczże mię, Panie! wyrwać; o Panie! na ratunek mój pospiesz.
Jẹ́ kí ó wù ọ́, ìwọ Olúwa, láti gbà mí là; Olúwa, yára láti ràn mí lọ́wọ́.
14 Niech będą pohańbieni, (a niech się zawstydzą wszyscy, ) którzy szukają duszy mojej, aby ją zatracili; niechajże się na wstecz cofną, a niech się zawstydzą, którzy mi życzą złego.
Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì kí wọn kí ó sì dààmú; àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n, àwọn tí ń wá ìpalára mi.
15 Niech będą spustoszeni za to, ze mię shańbić usiłują, mówiąc mi: Ehej! ehej!
Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!” ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
16 Ale niech się rozradują i rozweselą w tobie wszyscy, którzy cię szukają, i miłują zbawienie twoje; niech mówią zawżdy: Niechaj będzie Pan uwielbiony.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ kí ó máa yọ̀ kí inú wọn sì máa dùn sí ọ; kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ kí o máa wí nígbà gbogbo pé, “Gbígbéga ni Olúwa!”
17 Jamci wprawdzie ubogi i nędzny; aleć Pan myśli o mnie. Tyś jest pomocnikiem moim i wybawicielem moim; Boże mój! nie omieszkujże.
Bí ó ṣe ti èmi ni, tálákà àti aláìní ni èmi, ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi àti ìgbàlà mi; má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́, ìwọ Ọlọ́run mi.

< Psalmów 40 >