< Psalmów 38 >

1 Psalm Dawidowy ku przypominaniu. Panie! w popędliwości twojej nie nacieraj na mię, a w gniewie twoim nie karz mię.
Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
2 Albowiem strzały twoje utknęły we mnie, a ręka twoja dolega mię.
Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
3 Niemasz nic całego w ciele mojem dla rozgniewania twego; niemasz odpoczynku kościom moim dla grzechu mojego.
Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
4 Bo nieprawości moje przycisnęły głowę moję; jako brzemię ciężkie obciążyły mię.
Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
5 Zjątrzyły się, i pogniły rany moje, dla głupstwa mojego.
Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
6 Skurczyłem się, i skrzywiłem się bardzo, na każdy dzień w żałobie chodzę.
Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
7 Albowiem wnętrzności moje pełne są brzydkości, a nie masz nic całego w ciele mojem.
Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
8 Zemdlałem, i startym jest bardzo, ryczę dla trwogi serca mego.
Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
9 Panie! przed tobą jest wszystka żądość moja, a wzdychanie moje przed tobą nie jest skryte.
Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
10 Serce moje skacze; opuściła mię siła moja, a jasności oczów moich nie masz przy mnie.
Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
11 Którzy mię miłują, i przyjaciele moi, stronią od ran moich, a powinowaci moi z daleka stoją.
Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
12 I zastawili sidła ci, którzy szukają duszy mojej; a którzy mi szukają złego, mówili przewrotnie, i zdrady przez cały dzień zmyślali.
Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
13 Alem ja niby głuchy nie słyszał, a jako niemy, który ust swoich nie otwiera.
Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
14 I stałem się jako człowiek, który nic nie słyszy, i niema odporu w ustach swoich.
Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
15 Albowiem na cię, Panie! oczekuję; ty za mię odpowiesz, Panie, Boże mój!
Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
16 Bom rzekł: Niechaj się nie cieszą ze mnie; gdyby szwankowała noga moja, niechaj się hardzie nie podnoszą przeciwko mnie.
Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
17 Bom ja upadku bliski, a boleść moja zawżdy jest przedemną.
Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
18 Owszem, nieprawość moję wyznaję, a frasuję się dla grzechu mojego.
Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
19 Ale nieprzyjaciele moi weselą się, zmacniają się, i rozmnażają się ci, którzy mię nienawidzą bez przyczyny:
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
20 A oddawając mi złem za dobre sprzeciwiają mi się, przeto, że naśladuję tego, co jest dobrego.
Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
21 Nie opuszczajże mię, Panie, Boże mój! nie oddalajże się odemnie.
Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
22 Pośpiesz na ratunek mój, Panie zbawienia mego!
Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.

< Psalmów 38 >