< Psalmów 37 >

1 Pieśń Dawidowa. Nie obruszaj się dla złośników, ani zajrzyj czyniącym nieprawość.
Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
2 Bo jako trawa prędko podcięci będą, a jako liście zielone opadną.
nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
3 Ufaj w Panu, a czyń dobrze; mieszkajże na ziemi, a żyw się sprawiedliwie.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
4 Kochaj się w Panu, a dać prośby serca twego,
Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
5 Spuść na Pana drogę twoję, a ufaj w nim, a on wszystko uczyni;
Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
6 I wywiedzie jako światłość sprawiedliwość twoję, a sąd twój jako południe.
Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
7 Poddaj się Panu, a oczekuj go; nie obruszaj się na tego, któremu się szczęści w sprawach jego, na człowieka, który dokazuje, cokolwiek zamyśli.
Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
8 Przestań gniewu, a zaniechaj popędliwości; nie zapalaj się gniewem, abyś miał źle czynić.
Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
9 Albowiem złośnicy będą wykorzenieni: lecz którzy oczekują Pana, ci odziedziczą ziemię.
Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
10 Po małej chwili alić niemasz niezbożnika; spojrzyszli na miejsce jego, alić go już niemasz.
Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
11 Lecz pokorni odziedziczą ziemię, i rozkochają się w wielkości pokoju.
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
12 Zle myśli niepobożny przeciwko sprawiedliwemu, i zgrzyta nań zębami swemi.
Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
13 Ale się Pan śmieje z niego; bo widzi, że przychodzi dzień jego.
ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
14 Miecza dobyli niezbożni, a naciągnęli łuk swój, aby porazili ubogiego, i niedostatecznego, ażeby pomordowali tych, którzy chodzą prostą drogą;
Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
15 Aleć miecz ich przeniknie serce ich, a łuki ich będą połamane.
Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
16 Lepsza jest trocha sprawiedliwego, niż wielkie bogactwa wielu niepobożnych;
Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
17 Albowiem ramiona niezbożników będą pokruszone; ale sprawiedliwych Pan podpiera.
nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
18 Zna Pan dni doskonałych; przetoż dziedzictwo ich na wieki zostanie.
Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
19 Nie będą zawstydzeni we zły czas, a we dni głodu będą nasyceni;
Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
20 Ale niezbożni poginą, a nieprzyjaciele Pańscy, jako tłustość barania z dymem niszczeje, tak oni zniszczeją.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
21 Niezbożnik pożycza, a nie ma czem oddać; ale sprawiedliwy pokazuje łaskę, i rozdaje.
Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
22 Albowiem błogosławieni od Pana odziedziczą ziemię; ale przeklęci od niego będą wykorzenieni.
nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
23 Od Pana bywają sprawowane drogi człowieka dobrego, a droga jego, podoba mu się.
Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
24 Gdy padnie, nie stłucze się: albowiem Pan trzyma go za rękę jego.
bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
25 Byłem młodym, i zstarzałem się, nie widziałem sprawiedliwego opuszczonego, ani nasienia jego żebrzącego chleba.
Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
26 Na każdy dzień pokazuje miłosierdzie i pożycza, a przecież nasienie jego jest w błogosławieństwie.
Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
27 Odstąp od złego a czyń dobrze, a będziesz mieszkał na wieki.
Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
28 Albowiem Pan miłuje sąd, a nie opuści świętych swoich, na wieki w straży jego będą; ale nasienie niepobożnych będzie wykorzenione.
Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
29 Sprawiedliwi odziedziczą ziemię, i będą w niej mieszkali na wieki.
Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
30 Usta sprawiedliwego mówią mądrość, a język jego sąd opowiada.
Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
31 Zakon Boga jego jest w sercu jego; przetoż nie zachwieją się nogi jego.
Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
32 Wypatruje niepobożny sprawiedliwego, i szuka jakoby go zabił;
Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
33 Ale Pan nie zostawi go w ręku jego, i nie potępi go, gdy będzie sądzony.
Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
34 Oczekuj Pana, i strzeż drogi jego, a on cię wywyższy, abyś odziedziczył ziemię; a oglądasz, gdy niepobożni, wytraceni będą.
Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
35 Widziałem niezbożnika nader wyniosłego, a rozłożonego jako drzewo zielone samorosłe;
Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
36 Ale przeminął, a oto go nie było; szukałem go, alem go znaleść nie mógł.
ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
37 Spojrzyj na niewinnego, a przypatrz się szczeremu, że ostatnie rzeczy takiego człowieka są spokojne.
Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
38 Lecz przestępcy pospołu poginą, a niezbożnicy na ostatek wykorzenieni będą.
Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
39 Wszakże zbawienie sprawiedliwych jest od Pana, który jest mocą ich czasu uciśnienia.
Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
40 Wspomaga ich Pan, i wyrywa ich; wyrywa ich od niepobożnych, i zachowuje ich; bo w nim nadzieję mają.
Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

< Psalmów 37 >