< Psalmów 27 >

1 Psalm Dawidowy. Pan jest światłością moją, i zbawieniem mojem, kogóż się bać będę? Pan jest mocą żywota mego, kogóż się mam lękać?
Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
2 Gdy się zbiorą przeciwko mnie złośnicy, aby pożarli ciało moje; przeciwnicy moi, i nieprzyjaciele moi sami się potknęli i upadli.
Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
3 Przetoż choćby wojsko przeciwko mnie stanęło, nie ulęknie się serce moje; choćby powstała przeciwko mnie wojna, przecież ja w tym ufam.
Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
4 O jednem rzecz prosił Pana, i tej szukać będę; abym mieszkał w domu Pańskim po wszystkie dni żywota mego, a żebym oglądał wdzięczność Pańską, i dowiadywał się w kościele jego.
Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
5 Bo mię skryje w dzień zły w przybytku swoim; zachowa mię w skrytości namiotu swego, a na skale wywyższy mię.
Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
6 A tak wywyższona będzie głowa moja nad nieprzyjaciołmi moimi, którzy są około mnie; i będę ofiarował w przybytku jego ofiary wykrzykania; będę śpiewał i chwały oddawał Panu.
Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
7 Wysłuchaj, Panie! głos mój, kiedy wołam, a zmiłuj się nademną, i wysłuchaj mię.
Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
8 O tobie przemyśla serce moje, któryś rzekł: Szukajcie twarzy mojej; przetoż twarzy twojej, Panie! szukać będę.
Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
9 Nie ukrywajże twarzy twojej przedemną, ani odrzucaj w gniewie sługi twego; tyś bywał ratunkiem moim, nie opuszczajże mię, ani mię odstępuj, Boże zbawienia mego.
Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
10 Choć ojciec mój, i matka moja opuścili mię, wszakże Pan przyjął mię.
Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
11 Naucz mię, Panie! drogi twojej, a prowadź mnie ścieżką dla tych, którzy mię podstrzegają.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
12 Niepodawajże mię na wolę nieprzyjaciół moich; albowiemci powstali przeciwko mnie świadkowie fałszywi, i ten, który tchnie okrucieństwem.
Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
13 Bym był nie wierzył, że mam oglądać dobroć Pańską w ziemi żyjących, źleby o mnie było.
Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
14 Oczekujże Pana, zmacniaj się, a on utwierdzi serce twoje; przetoż oczekuj Pana.
Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.

< Psalmów 27 >