< Psalmów 25 >

1 Psalm Dawidowy. Do ciebie, Panie! duszę moję podnoszę.
Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
2 Boże mój! w tobie ufam; niech nie będę zawstydzony, niech się nie weselą nieprzyjaciele moi ze mnie.
Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
3 A tak wszyscy, którzy oczekują ciebie, nie będą zawstydzeni; zawstydzeni będą bez przyczyny nieprawość czyniący.
Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
4 Panie! daj mi poznać drogi twe, ścieżek twoich naucz mię.
Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
5 Daj, abym chodził w prawdzie twojej, i naucz mię; boś ty jest Bóg zbawienia mego; ciebie oczekuję dnia każdego.
ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
6 Wspomnij na litości twoje, Panie! i na miłosierdzia twoje, które są od wieku.
Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
7 Grzechów młodości mojej, i przestępstw moich nie racz pamiętać; według miłosierdzia twego wspomnij na mię, dla dobroci twojej, Panie!
Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
8 Dobry i prawy jest Pan; przetoż drogi naucza grzeszników.
Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
9 Poprowadzi cichych w sądzie, a nauczy pokornych drogi swojej.
Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
10 Wszystkie ścieżki Pańskie są miłosierdzie i prawda tym, którzy strzegą przymierza jego, i świadectwa jego.
Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
11 Panie! dla imienia twego odpuść nieprawość moję, bo wielka jest.
Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
12 Jestże człowiek, co się boi Pana? Nauczy go drogi, którąby miał obrać.
Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
13 Dusza jego w dobrem przemieszkiwać będzie, a nasienie jego odziedziczy ziemię.
Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
14 Tajemnica Pańska objawiona jest tym, którzy się go boją, a przymierze swoje oznajmuje im.
Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
15 Oczy moje ustawicznie patrzą na Pana; albowiem on wywodzi z sieci nogi moje.
Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
16 Wejrzyjże na mię, a zmiłuj się nademną; bom jest nędzny i opuszczony.
Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
17 Utrapienia serca mego rozmnożyły się; z ucisków moich wywiedź mię.
Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
18 Obacz udręczenie moje, i pracę moję, a odpuść wszystkie grzechy moje.
Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
19 Obacz nieprzyjaciół moich, jako się rozmnożyli, a mają mię niesłusznie w nienawiści.
Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
20 Strzeż duszy mojej, a wyrwij mię, abym nie był pohańbiony; bo w tobie nadzieję mam.
Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
21 Niewinność i szczerość niech mię strzegą; bom na cię oczekiwał.
Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
22 O Boże! wybawże Izraela ze wszystkich ucisków jego.
Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!

< Psalmów 25 >