< Psalmów 118 >

1 Wysławiajcie Pana, albowiem dobry; albowiem na wieki trwa miłosierdzie jego;
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Rzecz teraz, Izraelu! że na wieki miłosierdzie jego.
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Rzecz teraz, domie Aaronowy! że na wieki miłosierdzie jego.
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 Rzeczcież teraz, którzy się boicie Pana, że na wieki miłosierdzie jego.
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 W ucisku wzywałem Pana; wysłuchał mię, i na przestrzeństwie postawił mię Pan.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 Pan jest zemną, nie będę się bał, żeby mi co uczynił człowiek.
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 Pan jest zemną między pomocnikami mymi; przetoż ja oglądam pomstę nad tymi, którzy mię mają w nienawiści.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 Lepiej mieć nadzieję w Panu, niżeli ufać w człowieku.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 Lepiej mieć nadzieję w Panu, niżeli ufać w książętach.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 Wszystkie narody ogarnęły mię; ale w imieniu Pańskim wygubiłem ich.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 Częstokroć mię ogarnęły; ale w imieniu Pańskiem wygubiłem ich.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 Ogarnęły mię jako pszczoły, ale zgasły jako ogień z ciernia; bo w imieniu Pańskiem wytraciłem ich.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 Bardzoś potężnie na mię nacierał, abym upadł; ale Pan poratował mię.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 Pan jest mocą moją, i pieśnią moją; on był moim wybawicielem.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 Głos wykrzykania i zbawienia w przybytkach sprawiedliwych, prawica Pańska dokazała mocy;
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 Prawica Pańska wywyższyła się; prawica Pańska dokazała mocy.
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 Nie umrę, ale będę żył, abym opowiadał sprawy Pańskie.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 Pokarałci mię Pan srodze; ale mię na śmierć nie podał.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Otwórzcie mi bramy sprawiedliwości, a wszedłszy w nie będę wysławiał Pana.
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 Tać jest brama Pańska, którą sprawiedliwi wchodzą.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 Tuć ja ciebie wysławiać będę; boś mię wysłuchał, i byłeś wybawicielem moim.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 Kamień, którzy odrzucili budujący, uczyniony jest głową węgielną.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 Od Pana się to stało, a jest dziwno w oczach naszych.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 Tenci to dzień, który uczynił Pan; rozweselmyż się, a rozradujmy się weń.
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 Proszę, Panie! zachowajże teraz; proszę Panie! zdarz teraz.
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Błogosławiony, który przychodzi w imię Pańskie; błogosławimy wam z domu Pańskiego.
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 Bógci Panem, onci nas oświecił; przywiążcie baranki powrozami ku ofierze aż do rogów ołtarza.
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 Tyś jest Bóg mój; przetoż cię wysławiać będę, Boże mój! wywyższać cię będę.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 Wysławiajcież Pana, albowiem jest dobry: albowiem na wieki miłosierdzie jego.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

< Psalmów 118 >