< Psalmów 105 >

1 Wysławiajcie Pana; ogłaszajcie imię jego; opowiadajcie między narodami sprawy jego.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Śpiewajcie mu, śpiewajcie mu psalmy, rozmawiajcie o wszystkich cudach jego.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Chlubcie się imieniem świętem jego; niech się weseli serce szukających Pana.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Szukajcież Pana i mocy jego; szukajcie oblicza jego zawsze.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Przypominajcie sobie dziwy jego, które czynił, cuda jego i sądy ust jego.
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Wy nasienie Abrahama, sługi jego! Wy synowie Jakóbowi, wybrani jego!
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Onci jest Pan, Bóg nasz, po wszystkiej ziemi sądy jego.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Pamięta wiecznie na przymierze swoje: na słowo, które przykazał aż do tysiącznego pokolenia;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Które postanowił z Abrahamem, i na przysięgę swą uczynioną Izaakowi.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Bo je postanowił Jakóbowi za ustawę, a Izraelowi za umowę wieczną.
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Mówiąc: Tobie dam ziemię Chananejską za sznur dziedzictwa waszego;
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Kiedy ich był mały poczet, prawie mały poczet, a jeszcze w niej byli przychodniami.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Przechodzili zaiste od narodu do narodu, a z królestwa innego ludu;
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Nie dopuszczał nikomu, aby im miał krzywdę czynić; nawet karał dla nich i królów, mówiąc:
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 Nie tykajcie pomazańców moich, a prorokom moim nie czyńcie nic złego.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Gdy przywoławszy głód na ziemię, wszystkę podporę chleba pokruszył.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Posłał przed nimi męża, który był za niewolnika sprzedany, to jest Józefa;
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Którego nogi pętami trapili, a żelazo ścisnęło ciało jego,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Aż do onego czasu, gdy się o nim wzmianka stała; mowa Pańska doświadczała go.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Posławszy król kazał go puścić; ten, który panował nad narodami, wolnym go uczynił.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Postanowił go panem domu swego, i książęciem nad wszystką dzierżawą swoją,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Aby władał i książętami jego według zdania duszy swojej, i starców jego mądrości nauczał.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Potem wszedł Izrael do Egiptu, a Jakób był gościem w ziemi Chamowej;
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Gdzie rozmnożył Bóg lud swój bardzo, i uczynił go możniejszym nad nieprzyjaciół jego.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Odmienił serce ich, iż mieli w nienawiści lud jego, a zmyślali zdrady przeciw sługom jego.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Posłał Mojżesza, sługę swego i Aarona, którego obrał;
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Którzy im przedłożyli słowa znaków jego, i cuda w ziemi Chamowej.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Posłał ciemności, i zaćmiło się, a nie byli odpornymi słowu jego.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Obrócił wody ich w krew, a pomorzył ryby w nich.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Wydała ziemia ich mnóstwo żab, i były w pałacach królów ich.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Rzekł, a przyszła rozmaita mucha, i mszyce we wszystkich granicach ich.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Dał grad miasto deszczu, ogień palący na ziemię ich.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Także potłukł winnice ich, i figi ich, a pokruszył drzewa w granicach ich.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Rzekł, a przyszła szarańcza, i chrząszczów niezliczone mnóstwo;
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 I pożarły wszelkie ziele w ziemi ich, a pojadły urodzaje ziemi ich.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Nawet pobił wszystko pierworodztwo w ziemi ich, początek wszystkiej siły ich.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Tedy ich wywiódł ze srebrem i ze złotem, a nie był nikt słaby między pokoleniem ich.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Radował się Egipt, gdy oni wychodzili; albowiem był przypadł na nich strach ich.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Rozpostarł obłok na okrycie ich, a ogień na oświecanie nocy.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Na żądanie ich przywiódł przepiórki, a chlebem niebieskim nasycił ich.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Otworzył skałę i wypłynęły wody, a płynęły po suchych miejscach jako rzeka.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Albowiem wspomniał na słowo świętobliwości swojej, które rzekł do Abrahama, sługi swego.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Przetoż wywiódł lud swój z weselem, a z śpiewaniem wybranych swoich.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 I podał im ziemię pogan, a posiedli prace narodów.
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 Aby zachowali ustawy jego, a prawa jego przestrzegali. Halleluja.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psalmów 105 >