< Psalmów 103 >

1 Psalm Dawidowy. Błogosław duszo moja Panu, i wszystkie wnętrzności moje imieniowi jego świętemu.
Ti Dafidi. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
2 Błogosławże duszo moja Panu, a nie zapominaj wszystkich dobrodziejstw jego.
Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
3 Który odpuszcza wszystkie nieprawości twoje; który uzdrawia wszystkie choroby twoje;
ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́ tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
4 Który wybawia od śmierci żywot twój; który cię koronuje miłosierdziem i wielką litością:
ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
5 Który nasyca dobrem usta twoje, a odnawia jako orła młodość twoję.
ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
6 Pan czyni, co sprawiedliwego jest, i sądy wszystkim uciśnionym.
Olúwa ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún gbogbo àwọn tí a ni lára.
7 Oznajmił drogi swe Mojżeszowi, a synom Izraelskim sprawy swoje.
Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
8 Miłosierny i litościwy jest Pan, nierychły do gniewu, i wielkiego miłosierdzia.
Olúwa ni aláàánú àti olóore, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
9 Nie będzie się na wieki wadził, a gniewu wiecznie chował.
Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
10 Nie według grzechów naszych obchodzi się z nami, ani według nieprawości naszych odpłaca nam.
Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́ bí àìṣedéédéé wa.
11 Albowiem jako są niebiosa wysokie nad ziemią, tak jest utwierdzone miłosierdzie jego nad tymi, którzy się go boją;
Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
12 A jako daleko jest wschód od zachodu, tak daleko oddalił od nas przestępstwa nasze.
Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
13 Jako ma litość ojciec nad dziatkami, tak ma litość Pan nad tymi, którzy się go boją.
Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
14 Onci zaiste zna, cośmy za ulepienie, pamięta, żeśmy prochem.
nítorí tí ó mọ dídá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
15 Dni człowiecze są jako trawa, a jako kwiat polny, tak kwitnie.
Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko, ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
16 Gdy nań wiatr powienie, aliści go niemasz, ani go więcej pozna miejsce jego.
afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀, kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
17 Ale miłosierdzie Pańskie od wieków aż na wieki nad tymi, którzy się go boją, a sprawiedliwość jego nad synami synów,
Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
18 Którzy strzegą przymierza jego, i pamiętają na przykazanie jego, aby je czynili.
sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
19 Pan na niebiosach utwierdził stolicę; a królestwo jego nad wszystkimi panuje.
Olúwa ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run, ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
20 Błogosławcież Panu Aniołowie jego mocni w sile, którzy czynicie rozkazania jego, posłusznymi będąc głosowi słowa jego.
Yin Olúwa, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, tí ó ní ipá, tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
21 Błogosławcie Panu wszystkie wojska jego, słudzy jego, którzy czynicie wolę jego.
Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
22 Błogosławcie Panu wszystkie sprawy jego, na wszystkich miejscach panowania jego. Błogosław, duszo moja! Panu.
Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní ibi gbogbo ìjọba rẹ̀. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

< Psalmów 103 >