< Psalmów 10 >

1 Panie! przeczże stoisz z daleka? przeczże się ukrywasz czasu ucisku?
Èéha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré? Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?
2 Złośnik z hardości prześladuje ubogiego; niechajże będą uchwyceni w chytrych zamysłach, które zamyślają.
Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera, ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.
3 Bo się chlubi niezbożnik w pożądliwościach duszy swojej, a łakomy błogosławi sobie a draźni Pana.
Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀; Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn Olúwa.
4 Niepobożny dla pychy, którą po sobie pokazuje, nie pyta się o Boga; wszystka myśl jego, że niemasz Boga.
Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀; kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀.
5 Darzą mu się drogi jego na każdy czas; dalekie są sądy twoje od niego; sapa przeciwko wszystkim nieprzyjaciołom swym.
Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo; òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i; òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.
6 Mówi w sercu swem: Nie będę wzruszony od narodu do narodu; bo się nie boję złego.
O wí fún ara rẹ̀, “Kò sí ohun tí ó lè mì mí. Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà.”
7 Usta jego pełne są złorzeczeństwa, i chytrości, i zdrady; pod językiem jego uprzykrzenie i nieprawość.
Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ; wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.
8 Siedzi, czyhając we wsiach, w skrytościach zabija niewinnego; oczy jego upatrują ubogiego.
Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò. Ò gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀. Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.
9 Czyha w skrytem miejscu, jako lew w jamie swojej; dybie jakoby uchwycił ubogiego, ułapiwszy go ciągnie do sieci swojej.
Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí; Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́; ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.
10 Przypada, przytula się, i rzuca się mocą swoją na wiele ubogich.
Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀; kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.
11 Mówi w sercu swem: Zapomnałci tego Bóg; zakrył oblicze swoje, nie ujrzy na wieki.
Ó wí fún ara rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé; Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé.”
12 Powstańże, Panie Boże! podnieś rękę twoję; nie zapominajże ubogich.
Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run. Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.
13 Przeczże niezbożnik draźni Boga, mówiąc w sercu swem: Nie będziesz się o tem pytał?
Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run? Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀, “Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò”?
14 Ale ty widzisz ucisk, i krzywdę upatrujesz, abyś im odpłacił ręką twą; na ciebieć się spuścił ubogi, tyś jest pomocnikiem sierocie.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora; Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ. Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ; Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.
15 Potrzyj ramię niepobożnego i złośnika, dowiaduj się o jego niezbożności, aż go nie stanie.
Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi; pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀ tí a kò le è rí.
16 Pan jest królem na wieki wieczne; ale narody zginą z ziemi jego.
Olúwa ń jẹ ọba láé àti láéláé; àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.
17 Żądości pokornych wysłuchiwasz, Panie! utwierdzasz serca ich, nachylasz ku nim ucha twojego.
Ìwọ́ gbọ́, Olúwa, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára; Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,
18 Abyś sąd uczynił sierocie i chudzinie, aby go więcej nie trapił człowiek śmiertelny na ziemi.
láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára, kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé, kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.

< Psalmów 10 >