< Przysłów 21 >

1 Serce królewskie jest w ręce Pańskiej jako potoki wód; kędy chce, nakłoni je.
Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa; a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.
2 Wszelka droga człowieka prosta jest przed oczyma jego; ale Pan, jest który serca waży.
Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀, ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.
3 Czynić sprawiedliwość i sąd, bardziej się Panu podoba, niżeli ofiara.
Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.
4 Wyniosłość oczu i nadętość serca, i oranie niepobożnych są grzechem.
Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga, ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!
5 Myśli pracowitego pewne dostatki przynoszą; ale każdego skwapliwego przynoszą pewną nędzę.
Ètè àwọn olóye jásí èrè bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.
6 Zebrane skarby językiem kłamliwym są marnością pomijającą tych, którzy szukają śmierci.
Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́ jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.
7 Drapiestwo niezbożnych potrwoży ich; bo nie chcieli czynić to, co było sprawiedliwego.
Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ, nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
8 Mąż, którego droga przewrotna, obcym jest; ale sprawa czystego jest prosta.
Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.
9 Lepiej jest mieszkać w kącie pod dachem, niżeli z żoną swarliwą w domu przestronnym.
Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.
10 Dusza niezbożnego pragnie złego, a przyjaciel jego nie bywa wdzięczny w oczach jego.
Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Gdy karzą naśmiewcę, prostak mędrszym bywa; a gdy roztropnie postępują z mądrym, przyjmuje naukę.
Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n, nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.
12 Bóg daje przestrogę sprawiedliwemu na domie niezbożnika, który podwraca niezbożnych dla złości ich.
Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.
13 Kto zatula ucho swe na wołanie ubogiego, i on sam będzie wołał, a nie będzie wysłuchany.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú, òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú; ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.
14 Dar potajemnie dany uśmierza zapalczywość, i upominek w zanadrza włożony gniew wielki uspokaja.
Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò: àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá, dẹ́kun ìbínú líle.
15 Radość się mnoży sprawiedliwemu, gdy się sąd odprawuje; ale strach tym, którzy czynią nieprawość.
Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́: ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
16 Człowiek błądzący z drogi mądrości w zebraniu umarłych odpoczywać będzie.
Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye, yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
17 Mąż, który dobrą myśl miłuje, staje się ubogim; a kto miłuje wino i olejki, nie zbogaci się.
Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà: ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.
18 Niezbożnik będzie okupem za sprawiedliwego, a za uprzejmych przewrotnik.
Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo, àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.
19 Lepiej mieszkać w ziemi pustej, niż z żoną swarliwą i gniewliwą.
Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.
20 Skarb pożądany i olej są w przybytku mądrego; ale głupi człowiek pożera go.
Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n; ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.
21 Kto naśladuje sprawiedliwości i miłosierdzia, znajduje żywot, sprawiedliwość i sławę.
Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè, òdodo, àti ọlá.
22 Mądry ubiega miasto mocarzy, a burzy potęgę ufności ich.
Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára, ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.
23 Kto strzeże ust swoich i języka swego, strzeże od ucisków duszy swojej.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́, ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.
24 Hardego i pysznego imię jest naśmiewca, który wszysko poniewoli i z pychą czyni.
Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀, àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.
25 Leniwego żądość zabija; bo ręce jego robić nie chcą.
Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé; nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
26 Każdego dnia pała pożądliwością; ale sprawiedliwy udziela, a nie szczędzi.
Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́: ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.
27 Ofiara niepobożnych jest obrzydliwością, a dopieroż gdyby ją w grzechu ofiarował.
Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni: mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?
28 Świadek fałszywy zaginie; ale mąż dobry to, co słyszy, statecznie mówić będzie.
Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé: ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.
29 Mąż niezbożny zatwardza twarz swoję; ale uprzejmy sam sprawuje drogę swoję.
Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le: ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
30 Niemasz mądrości, ani rozumu, ani rady przeciwko Panu.
Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye, tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.
31 Konia gotują na dzień bitwy; ale od Pana jest wybawienie.
A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun: ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.

< Przysłów 21 >