< Przysłów 11 >

1 Waga fałszywa obrzydliwością jest Panu; ale gwichty sprawiedliwe podobają mu się.
Olúwa kórìíra òsùwọ̀n èké, ṣùgbọ́n òsùwọ̀n òtítọ́ jẹ́ inú dídùn un rẹ̀.
2 Za pychą przychodzi hańba; ale przy pokornych jest mądrość.
Nígbà tí ìgbéraga bá dé, nígbà náà ni ìdójútì dé, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ ni ọgbọ́n ń wá.
3 Szczerość ludzi cnotliwych prowadzi ich; ale przewrotność przestępców potraci ich.
Òtítọ́ inú ẹni dídúró ṣinṣin ń ṣe amọ̀nà rẹ̀, ṣùgbọ́n aláìṣòótọ́ yóò parun nípasẹ̀ àìṣòótọ́ wọn.
4 Niepomogą bogactwa w dzień gniewu; ale sprawiedliwość wybawia od śmierci.
Ọ̀rọ̀ kò níláárí ní ọjọ́ ìbínú, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
5 Sprawiedliwość uprzejmego sprawuje drogę jego; lecz bezbożny dla bezbożności swojej upada.
Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọn, ṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fà á lulẹ̀.
6 Sprawiedliwość uprzejmych wybawia ich: ale przewrotni w złościach pojmani bywają.
Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n là, ṣùgbọ́n ìdẹ̀kùn ètè búburú mú aláìṣòótọ́.
7 Gdy umiera człowiek niepobożny, ginie nadzieja jego, a oczekiwanie mocarzy niszczeje.
Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parun; gbogbo ohun tó ń fojú ṣọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já ṣófo.
8 Sprawiedliwy z ucisku wybawiony bywa; ale niepobożny przychodzi na miejsce jego.
A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibi dípò o rẹ̀, ibi wá sórí ènìyàn búburú.
9 Obłudnik usty kazi przyjaciela swego; ale sprawiedliwi umiejętnością wybawieni bywają.
Aláìmọ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ olódodo sá àsálà.
10 Z szczęścia sprawiedliwych miasto się weseli; a gdy giną niezbożni, bywa radość.
Nígbà tí olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀; nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.
11 Dla błogosławieństwa sprawiedliwych bywa wywyższone miasto; ale dla ust niepobożnych bywa wywrócone.
Nípasẹ̀ ìbùkún, olódodo a gbé ìlú ga: ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.
12 Głupi gardzi bliźnim swym; ale mąż roztropny milczy.
Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
13 Obmówca obchodząc objawia tajemnice; ale kto jest wiernego serca, tai zwierzonej rzeczy.
Olófòófó tú àṣírí ìkọ̀kọ̀ ṣùgbọ́n ẹni tó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a pa àṣírí mọ́.
14 Gdzie niemasz dostatecznej rady, lud upada; ale gdzie wiele radców, tam jest wybawienie.
Nítorí àìní ìtọ́sọ́nà orílẹ̀-èdè ṣubú ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn ìṣẹ́gun dájú.
15 Bardzo sobie szkodzi, kto za obcego ręczy; ale kto się chroni rękojemstwa, bezpieczen jest.
Ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ fún àlejò yóò rí ìyọnu, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kọ̀ láti ṣe onígbọ̀wọ́ yóò wà láìléwu.
16 Niewiasta uczciwa dostępuje sławy, a mocarze mają bogactwa.
Obìnrin oníwà rere gba ìyìn ṣùgbọ́n alágbára aláìbìkítà ènìyàn gba ọrọ̀ nìkan.
17 Człowiek uczynny dobrze czyni duszy swej; ale okrutnik trapi ciało swoje.
Ènìyàn rere ń ṣe ara rẹ̀ lóore ṣùgbọ́n ènìyàn ìkà ń mú ìyọnu wá sórí ara rẹ̀.
18 Niezbożnik czyni dzieło omylne; ale kto sieje sprawiedliwość, ma zapłatę trwałą.
Ènìyàn búburú gba èrè ìtànjẹ ṣùgbọ́n ẹni tó fúnrúgbìn òdodo yóò gba èrè tó dájú.
19 Jako sprawiedliwość jest ku żywotowi, tak kto naśladuje złości, bliski jest śmierci.
Olódodo tòótọ́ rí ìyè ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa ibi lé e sí ibi ikú ara rẹ̀.
20 Obrzydliwością są Panu przewrotni sercem; ale mu się podobają, którzy żyją bez zmazy.
Olúwa kórìíra àwọn ènìyàn ọlọ́kàn búburú ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn tí ọ̀nà wọn kò lábùkù.
21 Złośnik, choć sobie innych na pomoc weźmie, pomsty nie ujdzie; ale nasienie sprawiedliwych zachowane będzie.
Mọ èyí dájú pé, ènìyàn búburú kì yóò lọ láìjìyà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ láìjìyà.
22 Niewiasta piękna a głupia jest jako kolce złote w pysku u świni.
Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀ ni arẹwà obìnrin tí kò lọ́gbọ́n.
23 Żądza sprawiedliwych jest zawżdy ku dobremu; ale oczekiwanie niepobożnych, popędliwość.
Ìfẹ́ inú olódodo yóò yọrí sí ohun rere ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú yóò yọrí sí ìbínú.
24 Nie jeden udziela szczodrze, a wżdy mu przybywa; a drugi skąpi więcej niż trzeba, a wżdy ubożeje.
Ènìyàn kan ń fún ni lọ́fẹ̀ẹ́, síbẹ̀ ó ń ní sí i; òmíràn ń háwọ́ ju bí ó ti yẹ ṣùgbọ́n ó di aláìní.
25 Człowiek szczodrobliwy bywa bogatszy; a kto nasyca, sam też będzie nasycony.
Ẹni tí ń ṣoore yóò máa gbèrú sí i; ẹni tí ó tu ẹlòmíràn lára yóò ní ìtura.
26 Kto zatrzymuje zboże, tego lud przeklina; ale błogosławieństwo nad głową tego, który je sprzedaje.
Àwọn ènìyàn a ṣẹ́ èpè lé ènìyàn tí ń kó oúnjẹ pamọ́ ṣùgbọ́n ìbùkún a máa wá sórí ẹni tí ó ṣetán láti tà.
27 Kto pilnie szuka dobrego, nabywa przyjaźni; ale kto szuka złego, przyjdzie nań.
Ẹni tí ń lépa ohun rere yóò rí ohun rere ṣùgbọ́n ibi yóò dé bá ẹni tí ń lépa ibi.
28 Kto ufa w bogactwach swych, ten upadnie; ale sprawiedliwi jako latorośl zielenieć się będą.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóò ṣubú; ṣùgbọ́n olódodo yóò gbilẹ̀ bí i koríko tútù.
29 Kto czyni zamięszanie w domu swoim, odziedziczy wiatr, a głupi musi służyć mądremu.
Ẹni tí ó ń mú ìdààmú dé bá ìdílé rẹ̀ yóò jogún afẹ́fẹ́ lásán aláìgbọ́n yóò sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọlọ́gbọ́n.
30 Owoc sprawiedliwego jest drzewo żywota; a kto naucza ludzi, mądry jest.
Èso òdodo ni igi ìyè ẹni tí ó sì jèrè ọkàn jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
31 Oto jeźli się sprawiedliwemu na ziemi nagroda staje, tedy daleko więcej niezbożnemu i grzesznikowi.
Bí àwọn olódodo bá gba ìpín wọn lórí ilẹ̀ ayé mélòó mélòó ni ènìyàn búburú àti àwọn tó dẹ́ṣẹ̀!

< Przysłów 11 >