< Liczb 6 >

1 I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Powiedz synom Izraelskim, a mów do nich: Mąż albo niewiasta, gdy się odłączy, czyniąc ślub Nazarejstwa, aby byli odłączeni Panu,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
3 Od wina i mocnego napoju wstrzymywać się będzie; octu z wina, i octu z mocnego napoju pić nie będzie, i wszystkiego, co się z jagód wytłacza, nie będzie pił; także jagód winnych, świeżych ani suchych, jeść nie będzie.
irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
4 Po wszystkie dni Nazarejstwa swego ze wszystkiego, co wyrasta z macicy winnej, od ziarnka aż do łupiny, jeść nie będzie.
Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
5 Po wszystkie dni ślubu Nazarejstwa swego brzytwa nie postoi na głowie jego, aż wynijdzie czas, do którego się poświęcił Panu; będzie świętym, a zapuści włos na głowie swojej.
“‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
6 Po wszystkie dni, których się odłączy Panu, do umarłego nie wnijdzie.
“‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
7 Nad ojcem swym, i nad matką swą, nad bratem swym, i nad siostrą swą, nie splugawi się, gdyby zmarli; albowiem poświęcenie Boga swego ma na głowie swojej.
Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
8 Po wszystkie dni Nazarejstwa swego świętym będzie Panu.
Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
9 I gdyby kto umarł przy nim z prędka a nagle, i splugawiłby głowę poświęcenia jego, ogoli głowę swoję w dzień oczyszczenia swego; dnia siódmego ogoli ją.
“‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
10 A dnia ósmego przyniesie dwie synogarlice, albo dwoje gołąbiąt do kapłana ku drzwiom namiotu zgromadzenia;
Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
11 I będzie kapłan ofiarował jedno za grzech, a drugie na ofiarę całopalenia, i oczyści go od tego, czem zgrzeszył nad umarłym, a poświęci głowę jego dnia onego.
Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
12 Potem odłączy Panu dni Nazarejstwa swego, ofiarując baranka rocznego za występek; a dni one pierwsze daremne będą, gdyż splugawione było Nazarejstwo jego.
Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
13 A toć jest prawo Nazarejczyka: Gdy się wypełnią dni Nazarejstwa jego, przyjdzie do drzwi namiotu zgromadzenia,
“‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
14 I ofiarować będzie ofiarę swą Panu, baranka rocznego, zupełnego jednego na ofiarę całopalenia, i owcę jednę roczną i zdrową na ofiarę za grzech, i barana jednego zupełnego na ofiarę spokojną;
Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
15 Przytem kosz chlebów przaśnych, z mąki pszennej, placki zagniatane z oliwą, i kreple przaśne oliwą namazane, z ofiarą ich śniedną, i z ofiarą ich mokrą.
pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
16 I będzie ofiarował kapłan przed Panem, i uczyni ofiarę za grzech jego, i całopalenie jego.
“‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
17 Barana także ofiarować będzie na spokojną ofiarę Panu z koszem chlebów przaśnych; także ofiarować będzie kapłan ofiarę jego śniedną i ofiarę jego mokrą.
Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
18 I ogoli Nazarejczyk przede drzwiami namiotu zgromadzenia głowę Nazarejstwa swego, a wziąwszy włosy z głowy Nazarejstwa swego, włoży je na ogień, który jest pod ofiarą spokojną.
“‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
19 Przytem weźmie kapłan łopatkę warzoną baranią, i jeden placek przaśny z kosza, i jeden krepel niekwaszony, a da w ręce Nazarejczykowe po ogoleniu Nazarejstwa jego;
“‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 I będzie to tam i sam obracał kapłan na ofiarę obracania przed Panem; a rzecz ta poświęcona dostanie się kapłanowi, tak piersi obracania, jako i łopatka podnoszenia; a potem będzie mógł Nazarejczyk pić wino.
Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
21 Toć jest prawo Nazarejczyka, któryby ślub uczynił, i ta ofiara jego Panu za Nazarejstwo jego, okrom tego, coby więcej uczynić mógł; według ślubu swego, który uczynił, tak uczyni według prawa Nazarejstwa swego.
“‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
22 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 Mów do Aarona i do synów jego, a rzecz: Tak błogosławić będziecie synom Izraelskim, mówiąc do nich:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
24 Niech ci błogosławi Pan, a niechaj cię strzeże;
“‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
25 Niech rozjaśni Pan oblicze swoje nad tobą, a niech ci miłościw będzie;
Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
26 Niech obróci Pan twarz swoję ku tobie, a niechaj ci da pokój.
Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
27 I będą wzywać imienia mego nad synami Izraelskimi, a Ja im błogosławić będę.
“Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”

< Liczb 6 >