< Liczb 4 >

1 Nad to rzekł Pan do Mojżesza i Aarona, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Zbierz summę synów Kaatowych z pośród synów Lewiego według familii ich, i według domów ojców ich.
“Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
3 Od tego, który ma trzydzieści lat i wyżej, i aż do tego, co ma pięćdziesiąt lat, którzy będąc sposobnymi do tej pracy, mogliby odprawować posługę w namiocie zgromadzenia.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
4 Tać będzie powinność synów Kaatowych przy namiocie zgromadzenia, przy miejscu najświętszem;
“Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
5 I przyjdzie Aaron z synami swymi, gdy się będzie miał ruszyć obóz, a zdejmą oponę zasłony, i okryją nią skrzynię świadectwa;
Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
6 A włożą na nię przykrycie z borsukowych skór, i przykryją z wierzchu wszystko oponą hijacyntową, i założą drążki jej.
Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
7 Także stół chlebów pokładnych przykryją oponą hijacyntową, a położą na nim misy, i przystawki, i kubki, i czasze do nalewania; a chleb ustawicznie na nim będzie.
“Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
8 I rozciągną na tem oponę szarłatową, a przykryją to przykryciem skór borsukowych, i założą drążki do niego.
Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
9 Wezmą też oponę hijacyntową, którą nakryją świecznik do świecenia z lampami jego, i nożyczki jego, i kaganki jego, i wszystkie naczynia do oliwy jego, których używają przy nim:
“Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
10 I uwiną go ze wszystkiem naczyniem jego w przykrycie z skór borsukowych, i włożą na drążki.
Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
11 Na ołtarz także złoty rozpostrzą oponę hijacyntową, a włożą nań przykrycie z skór borsukowych, i założą drążki jego.
“Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
12 Pobiorą też wszystkie naczynia usługi, któremi służą w świątnicy, a obwinąwszy oponą hijacyntową, przykryją je przykryciem z skór borsukowych, i włożą na drążki.
“Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
13 Do tego zmiotą popiół z ołtarza, a na nim rozpostrzą oponę szarłatową;
“Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
14 I włożą nań wszystkie naczynia jego, któremi usługują przy nim, to jest łopaty, widły, i miotły, i kociełki, i wszystkie naczynia ołtarzowe, i rozpostrzą na nim przykrycie z skór borsukowych, i założą drążki jego.
Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
15 A gdy to wykona Aaron z synami swymi, że przykryje świątnicę ze wszystkiem naczyniem świątnicy, a będzie się miał ruszyć obóz, tedy potem przyjdą synowie Kaatowi, aby one rzeczy nieśli; ale się nie będą dotykali świątnicy, aby nie pomarli. Tać jest posługa synów Kaatowych, przy namiocie zgromadzenia.
“Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
16 Staranie zasię Eleazara, syna Aarona kapłana, będzie o oliwie do świecenia, o kadzeniu wonnem, o ofierze śniednej ustawicznej, i o olejku pomazywania, doglądanie przybytku, i wszystkiego, co w nim jest, i świątnicy z naczyniami jej.
“Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
17 Potem rzekł Pan do Mojżesza i Aarona, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
18 Nie zatracajcie pokolenia domów Kaatowych z pośrodku Lewitów.
“Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
19 Ale to im uczynicie, aby żyli a nie pomarli, gdy przystępować będą do miejsca najświętszego: Aaron i synowie jego przyjdą, i postanowią każdego z nich nad pracą jego i nad brzemieniem jego.
Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
20 Ale niech nie wchodzą patrzyć, gdy będą uwijane rzeczy święte, aby nie pomarli.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
21 Zatem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
22 Zbierz summę synów Gersonowych według domów ojców ich, i według familii ich;
“Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
23 Od tego, który ma trzydzieści lat i wyżej, aż do tego, który ma pięćdziesiąt lat, policzysz je, którzy sposobni będą do tej pracy, aby mogli usługować przy namiocie zgromadzenia.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
24 A tać będzie powinność domów synów Gersonowych ku posłudze i ku noszeniu.
“Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
25 Nosić będą opony przybytku, i namiot zgromadzenia z przykryciem jego; także przykrycie borsukowe, które z wierzchu na nim jest, i zasłonę od drzwi namiotu zgromadzenia;
Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
26 I opony do sieni, i zasłonę drzwi bramy u sieni, która jest u przybytku, i przy ołtarzu w około, i sznury jej, i wszystkie naczynia usługi ich, i wszystko, czego używają około usługi ich; i to czynić będą.
aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
27 Według rozkazania Aarona i synów jego będzie wszelka usługa synów Gersonowych przy każdem brzemieniu ich, i przy każdej usłudze ich; a poruczycie im pod straż wszystkie brzemiona ich.
Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
28 Tać będzie powinność domów synów Gersonowych w namiocie zgromadzenia, a będzie ich doglądał Itamar, syn Aarona kapłana.
Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
29 Syny także Merarego według familii ich, i według domów ojców ich policzysz:
“Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
30 Od tego, który ma trzydzieści lat i wyżej, i aż do tego, który ma pięćdziesiąt lat, policzysz je; którzy będąc sposobni do tej pracy mogliby usługować przy namiocie zgromadzenia.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
31 A ta będzie powinność pracy ich we wszystkiej usłudze ich w namiocie zgromadzenia: deski przybytku, i drągi jego, i słupy jego, i podstawki jego nosić;
Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
32 Przytem słupy sieni w około, i podstawki ich z kołkami ich, i sznury ich ze wszystkiem naczyniem ich, do wszelkiej służby ich; a mianowicie policzycie naczynia, które im poruczycie pod straż ich.
pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
33 Tać powinność będzie familii synów Merarego, według wszelkiej służby ich, przy namiocie zgromadzenia pod dozorem Itamara, syna Aarona kapłana.
Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
34 Obliczyli tedy Mojżesz i Aaron, i książęta zgromadzenia syny Kaatowe według familii ich, i według domów ojców ich.
Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
35 Od tych, którym było trzydzieści lat i wyżej, i aż do tych, którym było pięćdziesiąt lat, którzy sposobni będąc ku tej pracy mogliby usługować przy namiocie zgromadzenia.
Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
36 A było ich policzonych według familii ich dwa tysiące, siedem set i pięćdziesiąt.
Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
37 Cić byli policzeni z familii Kaatytów wszyscy służący przy namiocie zgromadzenia, które zliczył Mojżesz i Aaron według rozkazania Pańskiego przez Mojżesza.
Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
38 Także policzeni są synowie Gersonowi wedle familii swych, i według domów ojców swych,
Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
39 Od tego, który miał trzydzieści lat i wyżej, i aż do tego, który miał pięćdziesiąt lat, którzy sposobni będąc ku pracy mogli usługować przy namiocie zgromadzenia.
Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
40 A było ich policzonych według familii ich, i domów ojców ich dwa tysiące, sześć set i trzydzieści.
Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
41 Cić byli policzeni z familii synów Gersonowych, wszyscy służący w namiocie zgromadzenia, które zliczył Mojżesz i Aaron według słowa Pańskiego.
Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
42 Także policzeni z familii synów Merarego według familii swych i domów ojców swych,
Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
43 Od tego, który miał trzydzieści lat i wyżej, i aż do tego, który miał pięćdziesiąt lat; którzy sposobni będąc ku pracy mogli usługiwać przy namiocie zgromadzenia;
Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
44 A było ich policzonych według familii ich trzy tysiące i dwieście.
Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
45 A tać była summa policzonych z familii synów Merarego, które zliczył Mojżesz i Aaron według rozkazania Pańskiego przez Mojżesza.
Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
46 Wszystkich policzonych, które policzył Mojżesz i Aaron, i książęta Izraelskie z Lewitów według familii ich, i domów ojców ich,
Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
47 Od tego, który miał trzydzieści lat i wyżej, i aż do tego, który miał pięćdziesiąt lat, każdego przychodzącego do odprawowania powinności usługi, i powinności noszenia brzemion w namiocie zgromadzenia.
Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
48 A było ich policzonych osiem tysięcy, i pięć set i osiemdziesiąt.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
49 Według rozkazania Pańskiego policzeni są przez Mojżesza, każdy z osobna według usługi jego, i według brzemienia jego; a policzeni byli ci, które Pan rozkazał liczyć Mojżeszowi.
Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Liczb 4 >