< Liczb 33 >

1 Teć są ciągnienia synów Izraelskich, którzy wyszli z ziemi Egipskiej według hufów swych pod sprawą Mojżesza i Aarona.
Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
2 I spisał Mojżesz wychodzenia ich, i stanowiska ich według rozkazania Pańskiego. A teć są ciągnienia ich, i stanowiska ich:
Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
3 Naprzód wyciągnąwszy z Ramesses, miesiąca pierwszego, piętnastego dnia tegoż pierwszego miesiąca, nazajutrz po święcie przejścia, wyszli synowie Izraelscy ręką wyniosłą przed oczyma wszystkich Egipczanów;
Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
4 Gdy Egipczanie grzebli one, które był Pan między nimi pomordował, to jest, wszystko pierworodztwo, i gdy nad bogami ich wykonał Pan sądy.
Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
5 Ruszywszy się tedy synowie Izraelscy z Ramesses, położyli się obozem w Suchot.
Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
6 Ruszywszy się z Suchot, położyli się obozem w Etam, które jest przy końcu puszczy.
Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
7 A ruszywszy się z Etam, nawrócili się do Fihahyrot, które jest przeciw Baalsefon, i położyli się obozem przed Migdolem.
Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
8 A ruszywszy się z Fihahyrot, przeszli przez pośrodek morza na puszczą, i uszedłszy trzy dni drogi po puszczy Etam, położyli się obozem w Mara.
Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
9 A ruszywszy się z Mara, przyszli do Elim; a w Elim było dwanaście źródeł wód, i siedemdziesiąt drzew palmowych, i położyli się tam obozem.
Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
10 A ruszywszy się z Elim, położyli się obozem nad morzem czerwonem.
Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
11 A ruszywszy się od morza czerwonego, położyli się obozem na puszczy Syn.
Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
12 A ruszywszy się z puszczy Syn, położyli się obozem w Dafka.
Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
13 A ruszywszy się z Dafka, położyli się obozem w Alus.
Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
14 A ruszywszy się z Alus, położyli się obozem w Rafidym, gdzie nie miał lud wód dla napoju.
Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
15 A ruszywszy się z Rafidym, położyli się obozem na puszczy Synaj.
Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
16 A ruszywszy się z puszczy Synaj, położyli się obozem w Kibrot hataawa.
Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
17 A ruszywszy się z Kibrot hataawa, położyli się obozem w Hezerot.
Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
18 A ruszywszy się z Hezerot, położyli się obozem w Retma.
Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
19 A ruszywszy się z Retma, położyli się obozem w Remmon Fares.
Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
20 A ruszywszy się z Remmon Fares, położyli się obozem w Lebna.
Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
21 A ruszywszy się z Lebna, położyli się obozem w Ressa.
Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
22 A ruszywszy się z Ressa, położyli się obozem w Kieelata.
Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
23 A ruszywszy się z Kieelata, położyli się obozem na górze Sefer.
Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
24 A ruszywszy się z góry Sefer, położyli się obozem w Charada.
Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
25 A ruszywszy się z Charada, położyli się obozem w Makelot.
Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
26 A ruszywszy się z Makelot, położyli się obozem w Tahat.
Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
27 A ruszywszy się z Tahatu, położyli się obozem w Tare.
Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
28 A ruszywszy się z Tare, położyli się obozem w Metka.
Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
29 A ruszywszy się z Metka, położyli się obozem w Hesman.
Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
30 A ruszywszy się z Hesman, położyli się obozem w Moserot.
Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
31 A ruszywszy się z Moserot, położyli się obozem w Benejaakan.
Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
32 A ruszywszy się z Benejaakan, położyli się obozem w Horgidgad.
Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
33 A ruszywszy się z Horgidgad, położyli się obozem u Jotbata.
Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
34 A ruszywszy się z Jotbata, położyli się obozem w Habrona.
Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
35 A ruszywszy się z Habrona, położyli się obozem w Asyjongaber.
Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
36 A ruszywszy się z Asyjongaber, położyli się obozem na puszczy Syn, która jest Kades.
Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
37 A ruszywszy się z Kades, położyli się obozem na górze Hor, na granicach ziemi Edomskiej.
Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
38 Tedy wstąpił Aaron kapłan na górę Hor według rozkazania Pańskiego, i tam umarł roku czterdziestego po wyjściu synów Izraelskich z ziemi Egipskiej, miesiąca piątego, pierwszego dnia onego miesiąca.
Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
39 A miał Aaron sto dwadzieścia i trzy lat, gdy umarł na górze Hor.
Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
40 Tam usłyszał Chananejczyk, król Arad, który mieszkał na południe, w ziemi Chananejskiej, że ciągnęli synowie Izraelscy.
Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
41 A ruszywszy się z góry Hor, położyli się obozem w Salmona.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
42 A ruszywszy się z Salmona, położyli się obozem w Funon.
Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
43 A ruszywszy się z Funon, położyli się obozem w Obot.
Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
44 A ruszywszy się z Obot, położyli się obozem przy pagórkach Abarym, na granicy Moabskiej.
Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
45 A ruszywszy się z Abarym, położyli się obozem w Dybon Gat.
Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
46 A ruszywszy się z Dybon Gat, położyli się obozem w Helmon Dyblataim.
Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
47 A ruszywszy się z Helmon Dyblataim, położyli się obozem na górach Abarym, przeciwko Nebo.
Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
48 A ruszywszy się z gór Abarym, położyli się obozem na polach Moabskich, nad Jordanem, przeciw Jerychu.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
49 I tam się położyli nad Jordanem, od Betiesymot aż do Abelsytym, na polach Moabskich.
Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
50 I rzekł Pan do Mojżesza na polach Moabskich, nad Jordanem, przeciw Jerychu, mówiąc:
Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
51 Mów do synów Izraelskich, a powiedz im: Gdy przejdziecie za Jordan do ziemi Chananejskiej,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
52 Tedy wypędźcie wszystkie obywatele onej ziemi od oblicza waszego, i wytraćcie wszystkie malowania ich, i wszystkie obrazy bałwanów ich wygubcie, także wszystkie wyżyny ich spustoszcie.
lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
53 A wypędziwszy obywatele ziemi, mieszkać będziecie w niej; bom wam dał tę ziemię w dziedzictwo.
Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
54 I weźmiecie w dziedzictwo tę ziemię losem, według domów waszych; których więcej, tym większe dziedzictwo dacie, a których mniej, tym mniejsze dziedzictwo dacie, a które miejsce losem na kogo przypadnie, to mieć będzie; według pokolenia ojców waszych dziedzictwo brać będziecie.
Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
55 Ale jeźliż nie wypędzicie obywateli tej ziemi od oblicza waszego, tedy oni, które pozostawicie z nich, będą wam jako żądła w oczach waszych, i jako ciernie na boki wasze, i będą was trapić w tej ziemi, w której wy mieszkać będziecie.
“‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
56 I stanie się, że com umyślił onym uczynić, wam uczynię.
Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”

< Liczb 33 >