< Liczb 23 >

1 I rzekł Balaam do Balaka: Zbuduj mi tu siedem ołtarzów, a nagotuj mi tu siedem cielców, i siedem baranów;
Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
2 Uczynił tedy Balak, jako mówił Balaam, i ofiarował Balak z Balaamem cielca, i barana na każdym ołtarzu.
Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
3 Potem rzekł Balaam do Balaka: Stań przy całopaleniu twojem, a ja odejdę; owa się snać spotka Pan ze mną, a cokolwiek mi objawi, powiem ci; i odszedł sam.
Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
4 I spotkał się Pan z Balaamem; i rzekł mu Balaam: Postawiłem siedem ołtarzów, i ofiarowałem cielca i barana na każdym ołtarzu.
Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
5 Tedy Pan włożył słowa w usta Balaamowe, i rzekł: Wróć się do Balaka, a mów tak.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
6 I wrócił się do niego, a oto stał u ofiary swojej palonej, on i wszystkie książęta Moabskie.
Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
7 A tak zaczął przypowieść swoję, i rzekł: Z Aram przywiódł mię Balak, król Moabski, z gór wschodnich, mówiąc: Przyjdź, przeklinaj mi Jakóba, a przyjdź, złorzecz Izraelowi.
Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
8 Jakoż ja przeklinać mam, kogo Bóg nie przeklina? albo jako złorzeczyć mam, komu Pan nie złorzeczy?
Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
9 Bo z wierzchu skał oglądam go, a z pagórków będę nań patrzał; oto, lud ten sam mieszkać będzie, a między narody mieszać się nie będzie.
Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Któż policzy proch Jakóbów, i liczbę czwartej części Izraela? Niech umrze dusza moja śmiercią sprawiedliwych, i niech będzie dokonanie moje, jako ich.
Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
11 Tedy rzekł Balak do Balaama: Cóżeś mi uczynił? Na przeklinanie nieprzyjaciół moich przyzwałem cię, a oto, błogosławiąc błogosławiłeś im.
Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
12 A on odpowiedział i rzekł: Azaż nie mam tego pilnować i mówić, co Pan włożył w usta moje?
Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
13 I rzekł do niego Balak: Pójdź proszę ze mną na miejsce inne, żebyś go stamtąd widział; (ale tylko część jego ujrzysz, a wszystkiego widzieć nie będziesz; ) przeklinajże mi go stamtąd.
Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
14 I zawiódł go na pole Sofim, na wierzch góry Fazga, i zbudował siedem ołtarzów, i ofiarował cielca i barana na każdym ołtarzu.
Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
15 Rzekł tedy Balaam do Balaka: Zostań tu przy całopaleniu twojem, a ja zabieżę tam Panu.
Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
16 I zaszedł Pan Balaamowi, który włożył słowa w usta jego, i rzekł:
Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
17 Wróć się do Balaka, a tak mów. Przyszedł tedy do niego, a oto on stał przy całopaleniu swojem, i książęta Moabskie z nim; i rzekł mu Balak: Cóż ci powiedział Pan?
Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
18 I zaczął rzecz swą temi słowy: Wstań Balaku, a słuchaj: przyjmij w uszy swe słowa moje, synu Seforów.
Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
19 Nie jestci Bóg jako człowiek, aby kłamał, ani jako syn człowieczy, ażeby żałował; azaż on rzecze, a nie uczyni? wymówi, a nie wypełni?
Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
20 Otom wziął rozkazanie, abym błogosławił; on błogosławieństwo dał a ja go nie odwrócę.
Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
21 Nie baczy nieprawości w Jakóbie; ani widzi przestępstwa w Izraelu; Pan, Bóg jego, jest z nim, a trąbienie zwycięstwa królewskiego przy nim.
“Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
22 Bóg wywiódł je z Egiptu, mocą jednorożcową był mu.
Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
23 Albowiem nie masz wieszczby przeciw Jakóbowi, ani wróżki przeciw Izraelowi; od tego czasu mówiono będzie o Jakóbie i o Izraelu, co z nimi uczynił Bóg.
Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
24 Oto lud ten jako lew silny powstanie, jako lwię młode podniesie się, aż pożre łupy, i krew pobitych wypije.
Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
25 Tedy rzekł Balak do Balaama: Ani ich przeklinaj więcej, ani im też błogosław więcej.
Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
26 I odpowiedział Balaam, a rzekł do Balaka: Azażem ci nie powiadał, mówiąc, że cokolwiek mówić będzie Pan, to uczynię?
Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
27 I rzekł Balak do Balaama: Pójdź, proszę, zawiodę cię na insze miejsce, jeźli snać podoba się Bogu, żebyś je stamtąd przeklinał.
Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
28 Tedy wiódł Balak Balaama na wierzch góry Fegor, która patrzy ku puszczy.
Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
29 I rzekł Balaam do Balaka: Zbuduj mi siedem ołtarzów, a nagotuj mi tu siedem cielców i siedem baranów.
Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
30 I uczynił Balak, jako mu rozkazał Balaam, i ofiarował cielca i barana na każdym ołtarzu.
Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

< Liczb 23 >