< Liczb 17 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sì sọ fún Mose pé,
2 Mów do synów Izraelskich, a weźmij od nich po lasce według domów ojców ich, to jest, od wszystkich książąt ich według domów ojców ich, dwanaście lasek, a każdego imię napiszesz na lasce jego;
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì gba ọ̀pá méjìlá lọ́wọ́ wọn, ọ̀kọ̀ọ̀kan lọ́wọ́ olórí ìdílé ẹ̀yà ìran wọn, kọ orúkọ ènìyàn kọ̀ọ̀kan sí ara ọ̀pá rẹ̀.
3 Ale imię Aaronowe napiszesz na lasce Lewiego; bo każda laska będzie od każdego książęcia z domu ojców ich.
Lórí ọ̀pá Lefi kọ orúkọ Aaroni, nítorí ọ̀pá kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ wà fún olórí ìdílé kọ̀ọ̀kan tí yóò jẹ́ orí fún ẹ̀yà ìran kọ̀ọ̀kan.
4 I zostawisz je w namiocie zgromadzenia przed świadectwem, gdzie się z wami schodzę.
Kó wọn sí àgọ́ ìpàdé níwájú ẹ̀rí níbi tí èmi ti ń pàdé yín.
5 I stanie się, kogo obiorę, tego laska zakwitnie; i uśmierzę przed sobą szemrania synów Izraelskich, któremi szemrzą przeciwko wam.
Ọ̀pá tí ó bá yí jẹ́ ti ẹni tí èmi bá yàn yóò rúwé, èmi yóò sì dá kíkùn gbogbo ìgbà àwọn ọmọ Israẹli sí yín dúró.”
6 To gdy Mojżesz mówił do synów Izraelskich, oddali mu wszyscy książęta ich laski swoje, każdy książę laskę z domu ojca swego, dwanaście lasek; a laska Aaronowa była między laskami ich.
Nígbà náà Mose bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, àwọn olórí wọn sì fún un ní ọ̀pá méjìlá, ọ̀pá kan fún olórí kọ̀ọ̀kan ẹ̀yà ìran wọn, ọ̀pá Aaroni sì wà lára àwọn ọ̀pá náà.
7 I postawił mojżesz laski one przed Panem w namiocie świadectwa.
Mose sì fi ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú Olúwa nínú àgọ́ ẹ̀rí.
8 A gdy nazajutrz przyszedł Mojżesz do namiotu świadectwa, oto się zazieleniła laska Aaronowa z domu Lewiego, i wypuściła listki i wydała kwiat, i zrodziła dojrzałe migdały.
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kejì Mose wọ inú àgọ́ ẹ̀rí lọ, ó sì rí ọ̀pá Aaroni, tí ó dúró fún ẹ̀yà Lefi, kì í ṣe wí pé ó hù nìkan, ṣùgbọ́n ó rúwé, ó yọ ìtànná, ó sì so èso almondi.
9 I wyniósł Mojżesz one wszystkie laski od obliczności Pańskiej do wszystkich synów Izraelskich; które gdy ujrzeli, wziął każdy laskę swą.
Nígbà náà ni Mose kó gbogbo àwọn ọ̀pá jáde láti iwájú Olúwa wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wò wọ́n, ẹnìkọ̀ọ̀kan sì mú ọ̀pá tirẹ̀.
10 I rzekł Pan do Mojżesza: Odnieś laskę Aaronową przed świadectwo, aby była zachowana na znak synom odpornym, a zahamujesz szemranie ich przeciwko mnie, aby nie pomarli.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú ọ̀pá Aaroni padà wá síwájú ẹ̀rí, láti fi pamọ́ gẹ́gẹ́ bí àmì fún àwọn ọlọ̀tẹ̀. Èyí ó sì mú òpin bá kíkùn sínú wọn sí mi, kí wọn kí ó má ba à kú.”
11 I uczynił Mojżesz; jako mu Pan rozkazał, tak uczynił.
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti páláṣẹ fún un.
12 I rzekli synowie Izraelscy do Mojżesza, mówiąc: Oto umieramy, niszczejemy, wszyscy giniemy;
Àwọn ọmọ Israẹli sọ fún Mose pé, “Àwa yóò kú! A ti sọnù, gbogbo wa ti sọnù!
13 Każdy, ktokolwiek przystępuje do przybytku Pańskiego, umiera; izali do szczętu wytraceni być mamy?
Ẹnikẹ́ni tí ó bá súnmọ́ tabanaku Olúwa yóò kú. Ṣé gbogbo wa ni yóò kú?”

< Liczb 17 >