< Liczb 13 >

1 I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Poślij męże, którzy by przeszpiegowali ziemię Chananejską, którą Ja dawam synom Izraelskim; po jednym mężu z każdego pokolenia poślecie, którzy by byli przedniejsi między nimi.
“Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
3 Wysłał je tedy Mojżesz z puszczy Faran według rozkazania Pańskiego; a oni mężowie wszyscy byli co przedniejsi z synów Izraelskich.
Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
4 A teć są imiona ich: Z pokolenia Ruben Samua, syn Zachurów.
Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
5 Z pokolenie Symeonowego Safat, syn Hurów.
láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
6 Z pokolenia Judy Kaleb, syn Jefunów.
láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
7 Z pokolenia Isaschar Igal, syn Józefów.
láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
8 Z pokolenia Efraimowego Ozeasz, syn Nunów.
láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
9 Z pokolenia Benjaminowego Falty, syn Rafuów.
láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
10 Z pokolenia Zabulon Gedyjel, syn Sodego.
láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
11 Z pokolenia Józefowego, to jest z potomstwa Manasesowego, Gady, syn Susego.
láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
12 Z pokolenia Dan Ammijel, syn Gemmalego.
láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
13 Z pokolenia Aser Setur, syn Michaelów.
láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
14 Z pokolenia Neftali, Nabi, syn Wafsego.
láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
15 Z pokolenia Gad Guel, syn Machego.
láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
16 Teć są imiona mężów, które posłał Mojżesz na przeszpiegowanie ziemi: i nazwał Mojżesz Ozeasza, syna Nunowego, Jozue.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
17 A posyłając je Mojżesz na przeszpiegowanie ziemi Chananejskiej, mówił do nich: Idźcie w tę stronę ku południowi, a wnijdźcie na górę:
Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
18 I oglądajcie ziemię, jaka jest, i lud, który mieszka w niej, jeźli jest mocny, czyli mdły? jeźli ich mało, czyli wiele?
Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
19 Jaka też jest ziemia, w której mieszkają, jeźli dobra, czyli zła? i co są za miasta, w których mieszkają, jeźli w namieciech, czyli w obronnych miejscach?
Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
20 Także co za ziemia, jeźli urodzajna, czyli niepłodna? jeźli w niej są drzewa, czyli nie? a bądźcie mężnego serca i przynieście nam owocu tamtej ziemi; a było to w ten czas, gdy się wina dostawały.
Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
21 I szli, a przeszpiegowali ziemię od puszczy Syn aż do Rochob, którędy chodzą do Emat.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
22 A idąc ku południowi przyszli aż do Hebron, gdzie byli Ahiman, Sesai i Talmai, synowie Enakowi; a Hebron siedem lat było zbudowane przed Soan Egipskiem.
Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
23 Przyszli potem aż do rzeki Eschol, i urznęli tam gałąź z gronem jednem jagód winnych, i nieśli ją na drążku, dwa także granatowe jabłka i figi.
Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
24 I nazwano miejsce ono Nachal Eschol, od grona winnego, które tam byli urznęli synowie Izraelscy.
Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
25 Zatem wrócili się od onego szpiegowania ziemi po wyjściu czterdziestu dni.
Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
26 A wróciwszy się, przyszli do Mojżesza i do Aarona, i do wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich na puszczą Faran, która jest w Kades; i dali im i wszystkiemu pospólstwu sprawę, ukazawszy im owoc onej ziemi.
Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
27 A powiadali im, mówiąc: Przyszliśmy do ziemi, do którejś nas był posłał, która w prawdzie opływa mlekiem i miodem, a oto, ten jest owoc jej;
Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
28 Tylko że mocny jest lud, który mieszka w onej ziemi; miasta także obronne są, i bardzo wielkie; do tego i syny Enakowe tameśmy widzieli.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
29 Amalek mieszka w ziemi na południe, a Hetejczyk, i Jebuzejczyk, i Amorejczyk mieszka na górach; Chananejczyk zaś mieszka nad morzem, i nad brzegiem Jordanu.
Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
30 I hamował Kaleb lud szemrzący przeciw Mojżeszowi, i mówił: Pójdźmy a posiądźmy ziemię, bo ją pewnie sobie podbijemy.
Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
31 Ale mężowie oni, którzy z nim chodzili, rzekli: Nie będziem mogli ciągnąć przeciw tamtemu ludowi; bo mocniejszy jest nad nas.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
32 I zganili onę ziemię, którą byli przeszpiegowali, synom Izraelskim, mówiąc: Ziemia ta, którąśmy przeszli, i przeszpiegowali ją, jest ziemia pożerająca obywatele swoje, a lud wszystek, któryśmy w niej widzieli, lud jest wysokiego wzrostu.
Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
33 Tameśmy też widzieli olbrzymy, syny Enakowe z rodu olbrzymów; i zdaliśmy się sobie przy nich jako szarańcza, takimiż zdaliśmy się i onym.
A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”

< Liczb 13 >